< Isaiah 8 >

1 Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
LEUM GOD El fahk nu sik, “Eis sie ipin mwe sim lulap ac simusla fac ke mutun sim lulap: ‘Sulaklak Eisla, Aksaya Wapi.’
2 Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
Eis mwet lulalfongiyuk luo inge tuh elos in mwet loh: mwet tol Uriah, ac Zechariah wen natul Jeberechiah.”
3 Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Kutu pacl tok, mutan kiuk el pitutu ac oswela wen se. Na LEUM GOD El fahk nu sik, “Sang inel ‘Sulaklak-Eisla-Aksaya-Wapi.’
4 Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
Meet liki tulik mukul sac ku in fahk ‘Papa’ ac ‘Nina,’ mwe kasrup nukewa lun Damascus ac ma wap nukewa lun Samaria ac fah utukla sin tokosra lun Assyria.”
5 Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
LEUM GOD El sifilpa kaskas nu sik.
6 “Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
El fahk, “Ke sripen mwet inge srangesr eis kof mihs ma tuku ke Infacl srisrik Shiloah, a elos engan in eisalosyang nu inpaol Tokosra Rezin ac Tokosra Pekah,
7 ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
nga, LEUM GOD, ac fah use Tokosra Fulat lun Assyria ac un mwet mweun lal nukewa in mweun lain Judah. Elos ac fahsryak oana tuku lun sronot uh, oana kof lulap ke Infacl Euphrates, ac afunla pefacl uh.
8 yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
Elos ac asrma sasla Judah oana sie sronot ma lapak nu ke fulatan finpisen mwet uh, ac afunla ma nukewa.” God El wi kut! El karingin acn uh ye posohksok lal.
9 Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
Kowos mutunfacl uh, tukeni nu sie ke sangeng! Porongo, kowos su muta yen loessula faclu. Akola in mweun, tusruktu kowos in sangeng! Aok akola, tusruktu kowos in sangeng!
10 Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
Orala oakwuk lowos an, tusruktu ac fah tia ku in orekla. Fahk ma nukewa kowos lungse fahk, tusruktu ac wangin sripa, mweyen God El wi kut.
11 Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
Ke ku lulap lal, LEUM GOD El sensenkakinyu nga in tia fahsr ke inkanek ma mwet uh fahsr kac. El fahk,
12 “Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
“Nik kom wela pwapa sulal lun mwet, ac nik kom sangeng ke ma elos sangeng kac uh.
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
Esam lah nga, LEUM GOD Kulana, nga mutal. Nga pa kom ac sangeng se uh.
14 Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
Ke sripen mangoliyen mutal luk, nga oana sie eot ma mwet uh tukulkul kac. Nga oana sie sruhf ma ac srifusrya mwet in tokosrai lun Judah ac Israel, oayapa mwet Jerusalem.
15 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
Mwet puspis fah tukulkul. Elos ac ikori ac itungyuki. Elos ac fah sruh ac utukla.”
16 Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Kowos, mwet tumuk lutlut, enenu in karinganang ac sruokya ku kas nukewa ma God El ase nu sik.
17 Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
LEUM GOD El okanulla sifacna liki mwet lal uh, tuh nga lulalfongel ac filiya finsrak luk in El.
18 Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
Nga pa inge, wi tulik ma LEUM GOD El ase nu sik. LEUM GOD Kulana, su tron lal oan fin Eol Zion, El supwekut nu sin mwet Israel in oana mwe akul moul nu selos.
19 Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
Tusruktu mwet uh ac fah siyuk kom in lolngok yurin mwet susfa ac mwet inutnut, su ac mahma srisrik ac mungulngul. Elos fah fahk, “Ya tia fal mwet uh in sukok kas sin ngun, ac lolngok yurin mwet misa in kasru mwet moul?”
20 Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
Kowos in topkolos ac fahk, “Lipsre ma LEUM GOD El luti nu suwos! Nimet porongo mwet inutnut — ma elos fahk nu suwos uh ac tia ku in kasrekowos.”
21 Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
Mwet uh ac fufahsryesr fin facl sac, ac elos ac munasla ac masrinsralla. Ke sripen masrinsral lalos elos ac kasrkusrak ac selngawi tokosra lalos ac God lalos. Elos ac ngetak nu inkusrao,
22 Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.
ku suiya infohk uh, a wangin ma elos ac liye sayen mwe ongoiya ac lohsr matoltol — aok ac fah sisiyang elos nu in lohsr, ac wangin inkanek lalos in kaingla liki pacl in ongoiya se inge.

< Isaiah 8 >