< Isaiah 8 >

1 Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
L’Eternel me dit: "Prends une grande tablette et écris dessus en caractères lisibles pour la foule: proche est le pillage, imminente la déprédation."
2 Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
Je me fis assister de témoins dignes de foi, d’Urie le pontife et de Zacharie, fils de Yebérékhyahou.
3 Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Et je m’approchai de la prophétesse, qui conçut et enfanta un fils. Le Seigneur me dit: "Appelle-le du nom de Mahêr-Chalal Hach-Baz.
4 Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
Car l’enfant ne saura pas encore dire: Mon père, ma mère, que déjà on emportera devant le roi d’Assyrie les richesses de Damas et les dépouilles de Samarie."
5 Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
L’Eternel continua à me parler en ces termes:
6 “Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
"Puisque ce peuple a dédaigné les eaux de Siloé au cours paisible et vu avec plaisir Recen et le fils de Remalyahou,
7 ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
voici, le Seigneur dirigera contre eux les eaux puissantes et abondantes du Fleuve le roi d’Assyrie avec toutes ses forces; il montera par-dessus son lit et débordera sur toutes ses rives.
8 yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
Il se précipitera sur Juda, entraînant tout sur son passage, arrivant jusqu’au cou, et l’envergure de ses—ailes couvrira toute l’étendue de ton pays, ô Immanouel!"
9 Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
Agitez-vous bruyamment, peuples, vous serez brisés; entendez cela, ô contrées reculées de la terre, armez-vous, préparez-vous au combat, vous serez brisées!
10 Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
Concertez des plans: ils échoueront; annoncez des résolutions: elles ne tiendront pas. Car l’Eternel est avec nous.
11 Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
Car, ainsi me parla le Seigneur, avec une force impérieuse, en m’exhortant sévèrement de ne pas marcher dans la voie de ce peuple:
12 “Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
"N’Appelez point coalition ce que ce peuple appelle coalition, ne craignez pas ce qui cause sa terreur; n’en tremblez point."
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
C’Est l’Eternel-Cebaot que vous devez sanctifier; qu’il soit l’objet de vos craintes et de vos appréhensions.
14 Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
Il est un saint Refuge, mais il sera aussi une pierre d’achoppement, un écueil propre à faire trébucher pour les deux maisons d’Israël, un piège et un filet pour les habitants de Jérusalem.
15 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
Beaucoup d’entre eux s’y heurteront et se briseront en tombant; ils s’embarrasseront dans le filet et y resteront pris.
16 Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Il faut tenir secrète la leçon, mettre un sceau sur l’enseignement parmi mes disciples.
17 Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
J’Ai mis ma confiance en Dieu, qui voile présentement sa face à la maison de Jacob, et j’espère en lui.
18 Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
Voici, moi et les enfants que l’Eternel m’a donnés, nous servirons de signes et d’avertissements de la part de l’Eternel-Cebaot, qui réside sur le mont Sion.
19 Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
Que si l’on vous dit: "Allez consulter nécromanciens et devins, ceux qui chuchotent et marmottent; n’est-il pas vrai que tout peuple interroge son dieu? Qu’il s’adresse aux morts en faveur des vivants?"
20 Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
Tirez-en un enseignement, une leçon: assurément, on proférera des paroles de ce genre qui n’ont pas une lueur de raison.
21 Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
Aussi les gens circulent-ils dans le pays misérables et affamés; quand la faim les presse, ils s’emportent, maudissent leur roi et leur Dieu et se tournent vers le ciel.
22 Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.
Puis, ils regardent à terre, et voici, ce n’est que misère sombre, accablement et angoisses, et ténèbres sans limite.

< Isaiah 8 >