< Isaiah 8 >

1 Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Yahvé me dit: « Prends une grande tablette, et écris dessus avec une plume d'homme: « Pour Maher Shalal Hash Baz »;
2 Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
et je prendrai pour moi des témoins fidèles qui rendront témoignage: Urie, le prêtre, et Zacharie, fils de Jebérékia. »
3 Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Je suis allé vers la prophétesse; elle conçut et enfanta un fils. Et Yahvé me dit: « Appelle-le du nom de Maher Shalal Hash Baz ».
4 Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
Car avant que l'enfant sache dire: « Mon père » et « Ma mère », les richesses de Damas et le pillage de Samarie seront emportés par le roi d'Assyrie. »
5 Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
L'Éternel me parla encore, et dit:
6 “Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
Parce que ce peuple a refusé les eaux douces de Siloah, et qu'il s'est réjoui de Rezin et du fils de Remalia,
7 ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
voici que l'Éternel fait venir sur lui les eaux puissantes du fleuve: le roi d'Assyrie et toute sa gloire. Il montera par-dessus tous ses canaux, il franchira toutes ses rives.
8 yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
Il s'avance vers Juda. Il débordera et passera au travers. Elle atteindra jusqu'au cou. L'extension de ses ailes remplira la largeur de ton pays, Emmanuel.
9 Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
Faites du bruit, peuples, et soyez brisés! Écoutez, vous tous qui venez de pays lointains: habillez-vous pour la bataille, et soyez brisés! Habillez-vous pour le combat, et soyez brisés!
10 Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
Tenez conseil, et vous ne réussirez pas; prononcez la parole, et elle ne tiendra pas, car Dieu est avec nous. »
11 Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
Car Yahvé m'a dit cela d'une main ferme, et m'a recommandé de ne pas suivre la voie de ce peuple, en disant:
12 “Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
« N'appelle pas complot tout ce que ce peuple appelle complot. Ne crains pas leurs menaces et ne te laisse pas terroriser.
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
C'est Yahvé des Armées que vous devez respecter comme saint. C'est lui que vous devez craindre. C'est lui que tu dois redouter.
14 Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
Il sera un sanctuaire, mais pour les deux maisons d'Israël, il sera une pierre d'achoppement et un rocher qui les fera tomber. Pour les habitants de Jérusalem, il sera un piège et une embûche.
15 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
Beaucoup trébucheront sur lui, tomberont, seront brisés, seront pris au piège et seront capturés. »
16 Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Concluez l'alliance. Scelle la loi parmi mes disciples.
17 Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
J'attendrai Yahvé, qui cache sa face à la maison de Jacob, et je le chercherai.
18 Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
Voici, moi et les enfants que Yahvé m'a donnés, nous sommes pour des signes et des prodiges en Israël, de la part de Yahvé des armées, qui habite sur la montagne de Sion.
19 Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
Quand on vous dit: « Consultez ceux qui ont des esprits familiers et les sorciers, qui gazouillent et qui marmonnent », un peuple ne devrait-il pas consulter son Dieu? Ne doit-il pas consulter les morts au nom des vivants?
20 Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
Revenez à la loi et à l'alliance! S'ils ne parlent pas selon cette parole, il n'y aura pas de matin pour eux.
21 Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
Ils y passeront, très affligés et affamés. Il arrivera que, lorsqu'ils auront faim, ils s'inquiéteront et maudiront leur roi et leur Dieu. Ils tourneront leur visage vers le haut,
22 Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.
puis regarderont la terre et verront la détresse, les ténèbres et les ténèbres de l'angoisse. Ils seront poussés dans d'épaisses ténèbres.

< Isaiah 8 >