< Isaiah 8 >

1 Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Then Yahweh said to me, “Make a large signboard. And write clearly on it, ‘Maher-Shalal-Hash-Baz’ [which means ‘quickly (plunder/take by force) and steal everything’].”
2 Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
[So] I requested Uriah the [Supreme] Priest and Jeberekiah’s son Zechariah, men who were both honest/trustworthy witnesses, to watch me as I was doing that.
3 Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
Then I had sex with [EUP] [my wife, who was] a prophetess, and she became pregnant and [then] gave birth to a son. Then Yahweh said to me, “Give him the name Maher-Shalal-Hash-Baz (which means ‘suddenly attacked, quickly conquered’),
4 Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
because before he is old enough to say ‘papa’ or ‘mama’, the King of Assyria will [come with his army and] quickly take away all the valuable things in Damascus and in Samaria.”
5 Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
Yahweh spoke to me again and said, “[Tell the people of Judah, ]
6 “Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
‘[I have taken good care of] you people, but you have rejected that, [thinking that] my help was very little, like [MET] the little canal through which water flows from the Gihon Spring into Jerusalem. Instead, you have been happy [to request help from] King Rezin and King Pekah.
7 ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
Therefore, I will cause the people of Judah to be attacked by [the powerful army of] the King of Assyria, which will be [like] a great flood from the [Euphrates] River. Their soldiers will [be everywhere in your country, like] a river that overflows all its banks.
8 yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
Those soldiers will go all over Judah— [like a river whose water] [MET] rises as high as a person’s neck. Their army will spread over the land [quickly], like an eagle, and they will cover your entire land! But I will be with you!’”
9 Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
Listen, all you [people in] distant countries! [You can] prepare to attack Judah. [You can] prepare [for battle, and shout your] war-cries, but your [armies will] be crushed/shattered!
10 Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
[You can] prepare for what you will do [to attack Judah], but what you plan to do will not happen! You will not succeed, because God is with us!
11 Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
Yahweh strongly warned me [MTY] not to act like the [other] people in Judah did. He said to me,
12 “Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
“Do not say that everything that people do is conspiring/rebelling [against the government], like [other] people say, and do not (be afraid of/worry about) the things that other people are afraid of.
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
[I, ] the Commander of the armies of angels, am the one you should consider to be holy. And I am the one you should fear, the one you should revere.
14 Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
I will protect you(sg). [But as for] the [other] people [MTY] in Israel and Judah, I will be [like] [MET] a stone that causes people to stumble, a rock that causes them to fall down. [And as for] the people of Jerusalem, I will be [like] [MET] a trap or a snare [DOU].
15 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
Many [people] will stumble and fall down and never get up again. They will experience great troubles; they will be captured [by their enemies].”
16 Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
[So, I say to you who are my disciples], seal up this scroll on which I have written the messages that God has given to me, and give his instructions to [others] who have accompanied me.
17 Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
I will wait to see what Yahweh [will do]. He has rejected the descendants [MTY] of Jacob, but I will confidently expect him to help me.
18 Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
I and the children that Yahweh has given to me are [like] signs to warn [the people of] Israel; we are warnings from the Commander of the armies of angels the one who lives [in his temple] on Zion Hill [in Jerusalem].
19 Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
Some people may urge you(pl) to (consult/go and talk with) those who talk with the spirits of dead people or with those who say that they receive messages from those spirits. They whisper and mutter [about what we should do in the future]. But God is [RHQ] the one whom we should ask to guide us! It is ridiculous [RHQ] for people who are alive to request spirits of dead people to tell us [what we should do]!
20 Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
Pay attention to God’s instructions and teaching! If people do not say things that agree with what God teaches us, [what they say is worthless]. [It is as though] those people are in darkness.
21 Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
They will wander through the land, worried/discouraged and hungry. And when they become [very] hungry, they will become very angry. They will look up [toward heaven] and curse God and [will also] curse their king.
22 Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.
They will look around the land and see only trouble/distress and darkness and things that cause them to despair. And [then] they will be thrown into the very black darkness [of hell]. (questioned)

< Isaiah 8 >