< Isaiah 7 >

1 Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
Uzziya oğlu Yotam oğlu Ahaz Yahuda Kralı'yken, Aram Kralı Resin'le Remalya oğlu İsrail Kralı Pekah Yeruşalim'e saldırdılar, ama ele geçiremediler.
2 Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
Davut'un torunları Aram'ın Efrayimliler'le güçbirliği ettiğini duydular. Ahaz'la halkının yürekleri rüzgarda sallanan orman ağaçları gibi titremeye başladı.
3 Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
Bu arada RAB Yeşaya'ya şöyle seslendi: “Ahaz'ı karşılamak için oğlun Şear-Yaşuv'la birlikte Yukarı Havuz'un su yolunun sonuna, Çırpıcı Tarlası'na giden yola çık.
4 Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
Ona de ki, ‘Dikkatli ve sakin ol, korkma! Şu tüten iki yanık odun parçasının –Aram Kralı Resin'le Remalya'nın oğlunun– öfkesinden korkma.
5 Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
Aram, Efrayim ve Remalya'nın oğlu sizin için kötü şeyler tasarlıyor. Diyorlar ki,
6 “Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
Haydi, Yahuda'ya saldıralım, halkı korkutup ülkeyi ele geçirelim, Taveal'ın oğlunu kral ilan edelim.
7 Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
“‘Buna karşılık Egemen RAB diyor ki, bu tasarı asla gerçekleşmeyecek.
8 nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
Çünkü Şam sadece Aram'ın başkenti, Resin de sadece Şam'ın başıdır. Efrayim'e gelince, altmış beş yıl içinde paramparça edilip halk olmaktan çıkacak.
9 Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
Samiriye sadece Efrayim'in başkenti, Remalya'nın oğlu da sadece Samiriye'nin başıdır. Bana güvenmezseniz, güvenlikte olamazsınız.’”
10 Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
RAB Ahaz'a yine seslendi:
11 “Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol h7585)
“Tanrın RAB'den bir işaret iste; ölüler diyarı kadar derin, gökler kadar yüksek olsun.” (Sheol h7585)
12 Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
Ama Ahaz, “Hayır, istemem, RAB'bi sınamam” dedi.
13 Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
Bunun üzerine Yeşaya, “Dinleyin, ey Davut'un torunları!” dedi, “İnsanların sabrını taşırmanız yetmezmiş gibi şimdi de Tanrım'ın sabrını mı taşırıyorsunuz?
14 Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
Bundan ötürü Rab'bin kendisi size bir belirti verecek: İşte, kız gebe kalıp bir oğul doğuracak; adını İmmanuel koyacak.
15 Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
Çocuk kötüyü reddedip iyiyi seçecek yaşa gelince tereyağı ve bal yiyecek.
16 Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
Ama çocuk kötüyü reddedip iyiyi seçecek yaşa gelmeden, seni dehşete düşüren o iki kralın toprakları ıssız kalacak.
17 Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
“RAB seni, halkını ve babanın soyunu Efrayim'in Yahuda'dan ayrıldığı günden bu yana görülmemiş bir felakete uğratacak; üzerinize Asur Kralı'nı saldırtacak.
18 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
“O gün RAB Mısır ırmaklarının ta uçlarından sinekleri, Asur topraklarından arıları ıslıkla çağıracak.
19 Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
Akın akın gelip derin vadilerde, kaya kovuklarında, dikenli çalılıklarda, otlaklarda konaklayacaklar.
20 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
“O gün Rab Fırat'ın ötesinden kiraladığı usturayla –Asur Kralı'yla– sakalınızı, saçlarınızı, beden kıllarınızı tıraş edecek.
21 Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
O günlerde bir inekle bir çift koyun besleyen
22 Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
aldığı bol süt sayesinde tereyağı yiyecek. Ülkede kalan herkes bal ve tereyağıyla beslenecek.
23 Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
“O gün bin gümüş değerinde bin asmaya sahip olan her bağ dikenli çalılarla dolacak.
24 Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
İnsanlar oralara okla, yayla gidecek. Çünkü ülkenin her yanı dikenli çalılarla kaplanacak.
25 Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.
Bir zamanlar çapalanıp ekin ekilen tepeler korkudan kimsenin giremeyeceği dikenliklere dönecek, sığırın gezindiği, davarın çiğnediği yerler olacak.”

< Isaiah 7 >