< Isaiah 7 >

1 Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
Et dans les jours d'Achaz, fils de Joatham, fils d'Ozias, roi de Juda, il arriva que Rasin, roi d'Aram, et Phacée, fils de Romélie, roi d'Israël, marchèrent contre Jérusalem pour lui faire la guerre; mais ils ne purent la tenir assiégée.
2 Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
Et un message fut apporté en la maison de David, disant: Aram est coalisé avec Éphraïm. Et l'âme du roi fut saisie de stupeur, ainsi que l'âme de son peuple; comme dans une forêt les feuilles sont agitées par le vent.
3 Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
Et le Seigneur dit à Isaïe: Va à la rencontre d'Achaz, toi et ton fils Jasub qui te reste; prends le chemin d'en haut dans le champ du Foulon près la piscine;
4 Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
Et dis au roi: Tiens-toi en repos, et sois sans crainte; que ton âme ne soit pas abattue par ces deux bouts de tison qui fument; car, lorsque le transport de ma colère éclatera, je te guérirai encore une fois.
5 Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
Quant au fils d'Aram et au fils de Romélie, parce qu'ils ont conçu un mauvais dessein, disant:
6 “Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
Montons en Judée, et, nous liguant contre eux, soumettons-les à nous, et donnons-leur pour roi le fils de Tabéel;
7 Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
Voici ce que dit le Seigneur des armées: Ce complot ne subsistera pas, il ne s'accomplira point.
8 nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
Mais Damas restera la capitale de Syrie, et Rasin, roi de Damas. Et soixante-cinq ans encore, le royaume d'Éphraïm cessera d'être un peuple,
9 Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
Et Samarie, la capitale d'Éphraïm, et le fils de Romélie, la capitale de Samarie. Et si vous ne me croyez point, c'est que vous manquerez d'intelligence.
10 Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
Et le Seigneur continua de parler à Achaz, disant:
11 “Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol h7585)
Demande un signe au Seigneur ton Dieu, soit dans le ciel, soit dans l'abîme. (Sheol h7585)
12 Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
Et Achaz dit: Non, je ne demanderai rien, et je ne tenterai point le Seigneur.
13 Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
Et le Seigneur reprit: Écoutez donc, maison de David. Est-ce pour vous si peu de chose que de soutenir une lutte contre des hommes? Et comment soutiendrez-vous une lutte contre Dieu?
14 Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
C'est pourquoi le Seigneur lui-même vous donnera un signe. Voilà que la Vierge concevra dans son sein, et elle enfantera un fils, et tu lui donneras le nom d'Emmanuel.
15 Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
Il mangera du beurre et du miel, avant de savoir discerner le mal ou choisir le bien.
16 Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
Aussi même avant de connaître le bien et le mal, cet enfant rejettera le mal, pour choisir le bien. Et cette terre, que tu crains, elle sera abandonnée de la présence de ces deux rois.
17 Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
Et le Seigneur enverra sur toi, et sur ton peuple, et sur la maison de ton père, des jours tels qu'il n'en est point venu depuis le jour où Éphraïm a repoussé de Juda le roi des Assyriens.
18 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
Et voici ce qui arrivera: en ce jour le Seigneur sifflera pour appeler les mouches qui dominent sur une partie du fleuve d'Égypte, et les abeilles qui sont dans la région d'Assyrie.
19 Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
Et elles viendront toutes dans les vallons de la terre, et dans les creux des rochers, et dans les cavernes, et dans tous les ravins.
20 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
Ce jour-là, avec un rasoir loué sur les rives du fleuve du roi assyrien, le Seigneur rasera la tête de son peuple, et lui ôtera les poils de ses pieds et de sa barbe.
21 Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
Et en ce jour un homme à peine nourrira une vache et deux brebis.
22 Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
Et, au lieu de boire du lait en abondance, tout homme resté dans la contrée à peine y mangera du beurre et du miel.
23 Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
Et en ce jour il arrivera que tout lieu où il y aura eu des milliers de vignes, estimées des milliers de sicles, sera aride et couvert de ronces.
24 Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
On y entrera avec l'arc et la flèche, parce que toute la terre sera aride et couverte de ronces;
25 Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.
Et toute montagne jadis labourée sera inculte. Et la crainte ne l'envahira plus; car, à cause de son aridité et de ses ronces, ce ne sera plus qu'un pâturage pour les brebis et un passage pour les bœufs.

< Isaiah 7 >