< Isaiah 7 >

1 Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
II arriva, du temps d’Achaz, fils de Jotham, fils d’Ouzia, roi de Juda, que Recîn, roi de Syrie, de concert avec Pékah, fils de Remaliahou, roi d’Israël, marcha sur Jérusalem pour l’attaquer, mais ne put triompher d’elle.
2 Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
Quand la maison de David apprit cette nouvelle: "Le Syrien est venu camper avec Ephraïm," son cœur et le cœur de son peuple en frissonnèrent, comme les arbres d’une forêt frissonnent sous le vent.
3 Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
L’Eternel dit alors à Isaïe: "Rends-toi au-devant d’Achaz, toi et Chear-Yachoub, ton fils, vers l’extrémité du canal de la Piscine supérieure, sur la chaussée qui conduit au champ du Foulon.
4 Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
Et tu lui diras: N’Aie garde de perdre ton calme, sois sans crainte et ne laisse pas défaillir ton cœur devant ces deux bouts de tisons fumeux devant la colère de Recin et d’Aram, et du fils de Remaliahou.
5 Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
Puisque Aram a formé contre toi de mauvais desseins, ainsi qu’Ephraïm et le fils de Remaliahou, et qu’ils ont dit:
6 “Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
"Marchons contre Juda, réduisons-le à l’extrémité, forçons-le de se rendre à nous, puis nous lui imposerons comme roi le fils de Tabeal,"
7 Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
ainsi a parlé le Seigneur-Elohim: Cela ne s’accomplira ni ne sera!"
8 nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
Car la tête d’Aram, c’est Damas, et la tète de Damas, c’est Recin; (or dans soixante-cinq ans, Ephraïrn, déchu, cessera d’être une nation).
9 Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
Et la tête d’Ephraïm, c’est Samarie, et la tête de Samarie, c’est le fils de Remaliahou. Si vous manquez de confiance, vous manquerez d’avenir."
10 Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
L’Eternel, continuant de parler à Achaz, lui dit:
11 “Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol h7585)
"Demande un signe de la part de l’Eternel, ton Dieu, que ta demande s’applique aux régions d’en bas ou aux sphères supérieures. (Sheol h7585)
12 Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
Je n’en demanderai pas, répliqua Achaz: je ne veux pas mettre l’Eternel à l’épreuve."
13 Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
Alors le prophète reprit: "Ecoutez-donc, maison de David! Est-ce trop peu pour vous de lasser les hommes que vous vouliez encore lasser mon Dieu?
14 Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
Ah certes! Le Seigneur vous donne de lui-même un signe: Voici, la jeune femme est devenue enceinte, elle va mettre au monde un fils, qu’elle appellera Immanouel.
15 Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
Il se nourrira de crème et de miel, jusqu’à ce qu’il ait du discernement pour repousser le mal et choisir le bien.
16 Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
Or, avant même que l’enfant sache repousser le mal et choisir le bien, la région dont les deux rois te causent des angoisses sera devenue une solitude,
17 Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
le Seigneur suscitera contre toi, contre ton peuple et la maison de ton père des jours tels qu’il n’y en a pas eu depuis qu’Ephraïm s’est séparé de Juda et cela grâce au roi d’Assyrie.
18 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
En ce temps, le Seigneur appellera, par un sifflement, les moustiques qui sont sur les bords des canaux de l’Egypte et les frelons qui vivent en Assyrie;
19 Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
ils viendront s’abattre tous ensemble sur les vallons incultes, dans les fissures des rochers, dans tous les buissons et toutes les broussailles.
20 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
En ce jour, le Seigneur, au moyen du rasoir pris en location sur les bords du fleuve par l’entremise du roi d’Assyrie coupera les cheveux de la tête et les poils des jambes; il fera tomber la barbe elle-même.
21 Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
En ces temps, chaque individu pourra entretenir une génisse et deux brebis,
22 Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
et il en recueillera une telle quantité de lait qu’il se nourrira de crème. Oui, quiconque aura eu la vie sauve dans le pays pourra se nourrir de crème et de miel.
23 Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
Il arrivera encore, à la même époque, que tout terrain portant mille pieds de vigne d’une valeur de mille sicles, sera envahi par les ronces et les épines.
24 Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
On ne s’y rendra qu’armé de flèches et de carquois, tant le sol tout entier sera devenu la proie des ronces et des chardons.
25 Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.
Quant aux montagnes qu’on laboure au moyen de la bêche, on ne les abordera même pas, par crainte des ronces et des chardons; on y lâchera les bœufs, et elles seront foulées par les brebis.

< Isaiah 7 >