< Isaiah 7 >

1 Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
And in the dayes of Ahaz, the sonne of Iotham, the sonne of Vzziah king of Iudah, Rezin the King of Aram came vp, and Pekah the sonne of Remaliah King of Israel, to Ierusalem to fight against it, but he could not ouercome it.
2 Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
And it was tolde the house of Dauid, saying, Aram is ioyned with Ephraim: therefore his heart was moued, and the heart of his people, as the trees of the forest are moued by the winde.
3 Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
Then sayde the Lord vnto Isaiah, Goe foorth nowe to meete Ahaz (thou and Sheariashub thy sonne) at the ende of the conduit of the vpper poole, in the path of the fullers fielde,
4 Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
And say vnto him, Take heede, and be still: feare not, neither be faint hearted for the two tailes of these smoking firebrands, for the furious wrath of Rezin and of Aram, and of Remaliahs sonne:
5 Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
Because Aram hath taken wicked counsell against thee, and Ephraim, and Remaliahs sonne, saying,
6 “Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
Let vs goe vp against Iudah, and let vs waken them vp, and make a breach therein for vs, and set a King in the mids thereof, euen the sonne of Tabeal.
7 Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
Thus sayth the Lord God, It shall not stand, neither shall it be.
8 nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
For the head of Aram is Damascus, and the head of Damascus is Rezin: and within fiue and threescore yeere, Ephraim shalbe destroyed from being a people.
9 Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
And the head of Ephraim is Samaria, and the head of Samaria is Remaliahs sonne. If ye beleeue not, surely ye shall not be established.
10 Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
And the Lord spake againe vnto Ahaz, saying,
11 “Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol h7585)
Aske a signe for thee of the Lord thy God: aske it, either in the depth beneath or in the height aboue. (Sheol h7585)
12 Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
But Ahaz sayd, I wil not aske, neither will I tempt the Lord.
13 Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
Then he sayd, Heare you nowe, O house of Dauid, Is it a small thing for you to grieue men, that ye will also grieue my God?
14 Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
Therefore the Lord himselfe will giue you a signe. Beholde, the virgine shall conceiue and beare a sonne, and she shall call his name Immanu-el.
15 Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
Butter and hony shall he eate, till he haue knowledge to refuse the euill, and to chuse the good.
16 Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
For afore the childe shall haue knowledge to eschew the euill, and to chuse the good, the land, that thou abhorrest, shalbe forsaken of both her Kings.
17 Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
The Lord shall bring vpon thee, and vpon thy people, and vpon thy fathers house (the dayes that haue not come from the day that Ephraim departed from Iudah) euen the King of Asshur.
18 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
And in that day shall the Lord hisse for the flie that is at the vttermost part of the floods of Egypt, and for the bee which is in the lande of Asshur,
19 Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
And they shall come and shall light all in the desolate valleys, and in the holes of the rockes, and vpon all thorny places, and vpon all bushy places.
20 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
In that day shall the Lord shaue with a rasor that is hired, euen by them beyond the Riuer, by the King of Asshur, the head and the heare of the feete, and it shall consume the beard.
21 Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
And in the same day shall a man nourish a yong kow, and two sheepe.
22 Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
And for the abundance of milke, that they shall giue, hee shall eate butter: for butter and hony shall euery one eate, which is left within the land.
23 Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
And at the same day euery place, wherein shalbe a thousand vines, shalbe at a thousand pieces of siluer: so it shalbe for the briers and for the thornes.
24 Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
With arrowes and with bowe shall one come thither: because all the land shall be briers and thornes.
25 Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.
But on all the mountaines, which shalbe digged with the mattocke, there shall not come thither the feare of briers and thornes: but they shalbe for the sending out of bullocks, and for the treading of sheepe.

< Isaiah 7 >