< Isaiah 66 >

1 Báyìí ni Olúwa wí: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà? Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
Аша ворбеште Домнул: „Черул есте скаунул Меу де домние ши пэмынтул есте аштернутул пичоарелор Меле! Че касэ аць путя вой сэ-Мь зидиць ши че лок Мь-аць путя вой да ка локуинцэ?
2 Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?” ni Olúwa wí. “Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí: ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀, tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
Тоате ачесте лукрурь доар мына Мя ле-а фэкут ши тоате шь-ау кэпэтат астфел фиинца”, зиче Домнул. „Ятэ спре чине Ымь вой ындрепта привириле: спре чел че суферэ ши аре духул мыхнит, спре чел че се теме де Кувынтул Меу.
3 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ, dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá, ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí, dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà. Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n, ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn,
Чине ынжунгие ун боу ка жертфэ ну есте май бун декыт чел че учиде ун ом; чине жертфеште ун мел есте ка чел че ар рупе гытул унуй кыне, чине адуче ун дар де мынкаре есте ка чел че ар вэрса сынӂе де порк, чине арде тэмые есте ка чел че с-ар ынкина ла идоль; тоць ачештя ышь алег кэиле лор, ши суфлетул лор гэсеште плэчере ын урычуниле лор.
4 fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn. Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀. Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”
Де ачея ши Еу вой алеӂе че есте спре неферичиря лор ши вой адуче песте ей лукруриле де каре се тем, кэч, кынд ам кемат Еу, н-ау рэспунс ши, кынд ам ворбит Еу, н-ау аскултат, чи ау фэкут че есте рэу ынаинтя Мя ши ау алес че ну-Мь плаче!”
5 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín, tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé, ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo, kí a le rí ayọ̀ yín!’ Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
Аскултаць Кувынтул Домнулуй, вой, каре вэ темець де Кувынтул Луй: „Ятэ че зик фраций воштри, каре вэ урэск ши вэ изгонеск дин причина Нумелуй Меу: ‘Сэ-Шь арате Домнул слава, ка сэ вэ ведем букурия!’ Дар ей вор рэмыне де рушине!
6 Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá, gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá! Ariwo tí Olúwa ní í ṣe tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí wọn.
Ун глас рэсунэтор есе дин четате! Ун глас есе дин Темплу! Есте гласул Домнулуй, каре дэ врэжмашилор Луй плата кувенитэ!
7 “Kí ó tó lọ sí ìrọbí, ó ti bímọ; kí ó tó di pé ìrora dé bá a, ó ti bí ọmọkùnrin.
Ынаинте ка сэ симтэ дурерь, а нэскут ши, ынаинте ка сэ-й винэ суферинцеле, а дат наштере унуй фиу.
8 Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan? Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
Чине а аузит вреодатэ аша чева? Чине а вэзут вреодатэ аша чева? Се поате наште оаре о царэ ынтр-о зи? Се наште ун ням аша динтр-одатэ? Абя ау апукат-о мунчиле, ши фийка Сионулуй шь-а ши нэскут фиий!
9 Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí kí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ nígbà tí mo ń mú ìbí wá?” Ni Ọlọ́run yín wí.
Аш путя сэ дескид пынтечеле мамей ши сэ ну о лас сэ наскэ?”, зиче Домнул. „Еу, каре фак сэ наскэ, аш путя сэ ымпедик оаре наштеря?”, зиче Думнезеул тэу.
10 “Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀; ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
Букураци-вэ ымпреунэ ку Иерусалимул ши веселици-вэ ку ел, тоць чей че-л юбиць; ымпэрциць ши букурия ку ел, акум, тоць чей че л-аць плынс,
11 Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára, ẹ̀yin yóò mu àmuyó ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”
ка сэ фиць сэтураць бынд лаптеле мынгыерилор луй, ка сэ вэ десфэтаць ын тотул де плинэтатя славей луй.
12 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi; ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀ a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
Кэч аша ворбеште Домнул: „Ятэ, вой ындрепта спре ел пачя ка ун рыу ши слава нямурилор ка ун пырыу ешит дин маткэ ши вець фи алэптаць; вець фи пуртаць ын браце ши дезмердаць пе ӂенункь.
13 Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”
Кум мынгые пе чинева мама са, аша вэ вой мынгыя Еу; да, вець фи мынгыяць ын Иерусалим!
14 Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko; ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Ши кынд вець ведя ачесте лукрурь, инима ви се ва букура ши оаселе воастре вор принде путере ка ярба.” Домнул Ышь ва арэта астфел путеря фацэ де робий Сэй, дар ва фаче пе врэжмаший Луй сэ-Й симтэ мыния.
15 Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle; òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú, àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
Кэч ятэ, Домнул вине ынтр-ун фок ши кареле Луй сунт ка ун выртеж; Ышь префаче мыния ынтр-ун жэратик ши аменинцэриле, ын флэкэрь де фок.
16 Nítorí pẹ̀lú iná àti idà ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.
Кэч ку фок Ышь адуче Домнул ла ындеплинире жудекэциле ши ку сабия Луй педепсеште пе орьчине, ши чей учишь де Домнул вор фи мулць ла нумэр.
17 “Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.
„Чей че се сфинцеск ши се курэцеск ын грэдинь, мергынд унул кыте унул ын мижлокул челор че мэнынкэ ши карне де порк, ши шоаречь, ши алте лукрурь урычоасе, тоць ачея вор пери”, зиче Домнул.
18 “Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.
„Еу педепсеск фаптеле ши гындуриле лор! Дар вине время кынд вой стрынӂе тоате нямуриле ши тоате лимбиле; еле вор вени ши вор ведя слава Мя.
19 “Èmi yóò sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Ши вой пуне ун семн ынтре еле ши вой тримите ла нямурь пе чей че вор скэпа дин Исраел, ла Тарсис, ла Пул ши ла Луд, каре траг ку аркул, ла Тубал ши ла Иаван, ын остроавеле депэртате, каре н-ау аузит ворбинду-се ничодатэ де Мине ши н-ау вэзут слава Мя; ей вор вести слава Мя принтре нямурь.
20 Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ̀-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́.
Вор адуче пе тоць фраций воштри дин мижлокул тутурор нямурилор, ка дар Домнулуй, пе кай, ын каре ши пе тэрӂь, пе катырь ши пе дромадерь, ла мунтеле Меу чел сфынт, ла Иерусалим”, зиче Домнул, „кум ышь адук копиий луй Исраел даруриле де мынкаре, ынтр-ун вас курат, ла Каса Домнулуй.
21 Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.
Ши вой луа ши динтре ей пе уний ка преоць ши левиць”, зиче Домнул.
22 “Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé.
„Кэч дупэ кум черуриле челе ной ши пэмынтул чел ноу пе каре ле вой фаче вор дэйнуи ынаинтя Мя”, зиче Домнул, „аша вор дэйнуи ши сэмынца воастрэ ши нумеле востру.
23 Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí.
Ын фиекаре лунэ ноуэ ши ын фиекаре Сабат, ва вени орьче фэптурэ сэ се ынкине ынаинтя Мя”, зиче Домнул.
24 “Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”
„Ши, кынд вор еши, вор ведя трупуриле моарте але оаменилор каре с-ау рэзврэтит ымпотрива Мя, кэч вермеле лор ну ва мури ши фокул лор ну се ва стинӂе ши вор фи о причинэ де гроазэ пентру орьче фэптурэ.”

< Isaiah 66 >