< Isaiah 66 >

1 Báyìí ni Olúwa wí: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà? Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
diz Yahweh: “O céu é meu trono, e a terra é meu escabelo dos pés. Que tipo de casa você vai construir para mim? Onde vou descansar?
2 Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?” ni Olúwa wí. “Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí: ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀, tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
Pois minha mão fez todas essas coisas, e assim todas essas coisas vieram a ser”, diz Yahweh: “mas eu vou olhar para este homem, mesmo para aquele que é pobre e de espírito contrito, e que treme com a minha palavra.
3 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ, dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá, ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí, dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà. Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n, ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn,
Aquele que mata um boi é como aquele que mata um homem; aquele que sacrifica um cordeiro, como aquele que quebra o pescoço de um cão; aquele que oferece uma oferta, como aquele que oferece sangue de porco; aquele que queima incenso, como aquele que abençoa um ídolo. Sim, eles escolheram seus próprios caminhos, e sua alma se deleita em suas abominações.
4 fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn. Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀. Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”
Também vou escolher seus delírios, e trará seus medos sobre eles, porque quando eu liguei, ninguém atendeu; quando eu falei, eles não me ouviram, mas eles fizeram o que era mau aos meus olhos, e escolhi aquilo em que não me deleitei”.
5 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín, tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé, ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo, kí a le rí ayọ̀ yín!’ Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
Ouça a palavra de Yahweh, você que treme com sua palavra: “Seus irmãos que o odeiam você”, que o expulsaram por causa do meu nome, disseram, “Que Yahweh seja glorificado”, para que possamos ver sua alegria'. mas são aqueles que devem ficar desapontados.
6 Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá, gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá! Ariwo tí Olúwa ní í ṣe tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí wọn.
Uma voz de tumulto da cidade, uma voz do templo, uma voz de Yahweh que devolve a seus inimigos o que eles merecem.
7 “Kí ó tó lọ sí ìrọbí, ó ti bímọ; kí ó tó di pé ìrora dé bá a, ó ti bí ọmọkùnrin.
“Antes de sua viagem, ela deu à luz. Antes que sua dor chegasse, ela deu à luz um filho.
8 Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan? Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
Quem já ouviu falar de tal coisa? Quem já viu tais coisas? Nascerá uma terra em um dia? Nascerá uma nação de uma só vez? Pois assim que Zion chegou a Zion, ela deu à luz a seus filhos.
9 Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí kí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ nígbà tí mo ń mú ìbí wá?” Ni Ọlọ́run yín wí.
Devo levar para o nascimento, e não causar o parto?” diz Yahweh. “Devo eu fazer com que o útero feche?” diz seu Deus.
10 “Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀; ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
“Alegrem-se com Jerusalém, e alegrem-se por ela, todos vocês que a amam. Alegrem-se com ela, todos vocês que choram por ela;
11 Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára, ẹ̀yin yóò mu àmuyó ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”
para que você possa cuidar e ficar satisfeito com os seios reconfortantes; que você possa beber profundamente, e se encante com a abundância de sua glória”.
12 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi; ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀ a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
Para Iavé diz: “Eis que lhe estenderei a paz como um rio”, e a glória das nações como uma corrente transbordante, e você vai cuidar. Você será carregado do lado dela, e será afagada de joelhos.
13 Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”
Como alguém a quem sua mãe conforta, portanto, eu o consolarei. Você será consolado em Jerusalém”.
14 Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko; ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Você o verá e seu coração se regozijará, e seus ossos florescerão como a erva tenra. A mão de Yahweh será conhecida entre seus criados; e ele terá indignação contra seus inimigos.
15 Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle; òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú, àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
Pois, eis que Yahweh virá com fogo, e suas carruagens serão como o redemoinho; para tornar sua raiva feroz com ferocidade, e sua reprimenda com chamas de fogo.
16 Nítorí pẹ̀lú iná àti idà ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.
Pois Yahweh executará o julgamento pelo fogo e por sua espada sobre toda a carne; e os mortos por Javé serão muitos.
17 “Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.
“Aqueles que se santificam e se purificam para ir aos jardins, seguindo um no meio, comendo carne de porco, coisas abomináveis e o rato, chegarão ao fim juntos”, diz Yahweh.
18 “Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.
“Pois eu conheço seus trabalhos e seus pensamentos. Chegou a hora de reunir todas as nações e idiomas, e eles virão, e verão minha glória.
19 “Èmi yóò sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
“Eu colocarei um sinal entre eles, e enviarei aqueles que escaparem deles para as nações, para Társis, Pul e Lud, que desenham o arco, para Tubal e Javan, para ilhas distantes, que não ouviram a minha fama, nem viram a minha glória; e eles declararão a minha glória entre as nações.
20 Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ̀-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́.
Eles trarão todos os seus irmãos de todas as nações para uma oferta a Iavé, em cavalos, em carros, em ninhadas, em mulas e em camelos, à minha santa montanha Jerusalém, diz Iavé, enquanto os filhos de Israel trazem sua oferta em um vaso limpo para a casa de Iavé.
21 Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.
Deles também selecionarei sacerdotes e levitas”, diz Yahweh.
22 “Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé.
“Pois como os novos céus e a nova terra, que eu farei, permanecerão diante de mim”, diz Yahweh, “assim permanecerão sua descendência e seu nome”.
23 Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí.
Acontecerá que de uma lua nova a outra, e de um sábado a outro, toda a carne virá para adorar diante de mim”, diz Yahweh.
24 “Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”
“Eles sairão, e olharão para os cadáveres dos homens que transgrediram contra mim; pois seu verme não morrerá, nem seu fogo se apagará, e eles serão odiosos para toda a humanidade”.

< Isaiah 66 >