< Isaiah 66 >

1 Báyìí ni Olúwa wí: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà? Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Polo e koma mar duongʼ, to piny e raten tienda. Koro ere kama dugerna e ot? To kar yweyo mara nobed kanye?
2 Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?” ni Olúwa wí. “Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí: ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀, tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
Donge lweta ema osechweyo gigi duto momiyo gibedo mangima?” Jehova Nyasaye ema owacho. “Ma e ngʼat ma ayiego ma en ngʼat ma hore kendo man-gi chuny motur, kendo ngʼama oluoro wachna.
3 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ, dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá, ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí, dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà. Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n, ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn,
To ngʼato angʼata moyangʼo rwath katimogo misango chal gi ngʼat monego dhano, kendo ngʼato angʼata motimo misango mar rombo, chal gi ngʼama oturo ngʼut guok, kendo ngʼato angʼata mochiwo misango mar cham chal gi ngʼat mochiwo remb anguro, bende ngʼato angʼata mowangʼo ubani mangʼwe ngʼar mar rapar, chal gi ngʼama lamo nyiseche manono. Giseyiero yoregi giwegi kendo chunygi mor gi timbegi mag rondogo;
4 fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn. Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀. Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”
omiyo an bende abiro yieronegi masiche mondo omakgi kendo abiro kelo kuomgi gik ma giluoro. Nimar kane aluongo, to onge ngʼat mane odwoka, kendo kane awuoyo, to onge ngʼat mane owinjo. Negitimo timbe mamono e nyima, kendo ne giyiero mana gik mamorogi.”
5 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín, tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé, ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo, kí a le rí ayọ̀ yín!’ Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
Winjuru wach Jehova Nyasaye, un jogo matetni kuwinjo dwonde: “Oweteni mochai kendo ok kwani ka gimoro nikech ihero nyinga osewacho niya, ‘Mad Jehova Nyasaye mi duongʼ, mondo omi wane morni!’ Kata kamano gin giwegi ema ginine wichkuot.
6 Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá, gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá! Ariwo tí Olúwa ní í ṣe tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí wọn.
Winjuru kaka nduru wuok e dala maduongʼ, kendo winjuru kaka kokono wuok e hekalu! Ma en dwond Jehova Nyasaye kochulogo kuor ne wasike moromo gi timbegi.
7 “Kí ó tó lọ sí ìrọbí, ó ti bímọ; kí ó tó di pé ìrora dé bá a, ó ti bí ọmọkùnrin.
“Kapok muoch ochako kaye, to osenywolo nyathi; kapok owinjo rem to osenywolo wuowi.
8 Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan? Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
En ngʼa mosewinjo wach machal kamano? En ngʼa moseneno gik machalo kamano? Bende piny dichwe godiechiengʼ achiel koso ogendini dichok dichiel? To mana e seche mane muoch ochako kayo Sayun ema nonywoloe nyithinde.
9 Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí kí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ nígbà tí mo ń mú ìbí wá?” Ni Ọlọ́run yín wí.
Bende dawe sa ma dhako nywolie chopi mak amiye teko mar nywol?” Jehova Nyasaye owacho. “Bende dadin ich kochopo sa mar chiwo nyathi?” Nyasachi owacho.
10 “Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀; ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
“Moruru gi Jerusalem kendo bed mamor kode, un duto muhere; beduru gi ilo maduongʼ, un duto man-gi kuyo nikech en.
11 Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára, ẹ̀yin yóò mu àmuyó ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”
Nimar ibiro piru maber kudhodho thunde; kendo unumethi gi ilo mi ubed gi mor mogundho.”
12 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi; ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀ a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
Nimar ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Abiro miyo kwe ma en-go mol ka aora kendo mwandu mag pinje namiye mamol ka oula; unubed mamor ka odhodhou kotingʼou e bade kendo kopirou e chonge.
13 Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”
Mana kaka miyo hoyo nyathine, e kaka abiro hoyou; kendo noho chunyu e Jerusalem.”
14 Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko; ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Ka uneno ma, to chunyu nobed gi mor, kendo dendu nobed maber mana ka lum matwi ndalo chwiri; lwet Jehova Nyasaye nofwenyre ne jotichne, to mirimbe to none kuom wasike.
15 Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle; òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú, àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
To nee, Jehova Nyasaye biro gi mach, kendo gechene mag lweny chalo ka kalausi; obiro kelo mirimbe makakni, kendo chwat mare nopilre ka mach.
16 Nítorí pẹ̀lú iná àti idà ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.
Nimar mach kod ligangla ema Jehova Nyasaye noyalgo ji duto, kendo joma Jehova Nyasaye nonegi nobed mangʼeny.
17 “Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.
Jehova Nyasaye wacho niya, “Joma pwodhore kendo bedo maler mondo odhiye puothe, kamoro ka moro luwo wadgi kendo chamo ring anguro, oyieyo kod gik moko duto makwero norum duto dichiel.
18 “Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.
“An Jehova Nyasaye angʼeyo timbeni gi paroni achiegni biro mondo achok ogendini duto kod dhoudi mawacho dhok mopogore opogore kendo ginibi mi ginine duongʼ mara maler.
19 “Èmi yóò sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
“Anatim ranyisi e kindgi kendo anaor jomoko manok ma notony mane pok owinjo humba kata mane pok oneno duongʼ mara maler ma gin: Tarshish, Libya, Lud (mongʼere gi nying mar jolweny mongʼeyo kedo gi asere), jo-Tubal kod jo-Yunani kaachiel gi joma odak e dho nembe man kuonde maboyo. Gibiro nyiso duongʼna e kind ogendini.
20 Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ̀-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́.
Kendo ginikel oweteni duto koa e ogendini duto, e goda maler ma en Jerusalem kaka gir misango ne Jehova Nyasaye ka moko oidho farese, geche lweny, pundane kod ngamia,” Jehova Nyasaye owacho. “Gibiro kelogi mana kaka jo-Israel kelo misengini e od Jehova Nyasaye, ka gitingʼogi e tewni maler.
21 Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.
Kendo moko kuomgi bende nayier mondo obed jodolo kod jo-Lawi,” Jehova Nyasaye owacho.
22 “Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé.
Jehova Nyasaye wacho niya, “Mana kaka polo manyien machweyo gi piny manyien nosiki e nyima, e kaka nyingi kod nying nyikwayi nosiki.
23 Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí.
Mana kaka dwe por kendo podho kendo machielo por, bende mana kaka chiengʼ Sabato nyaka chiengʼ Sabato machielo e kaka ji duto biro bedo kendo kulore e nyima,” Jehova Nyasaye owacho.
24 “Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”
“Giniwuogi mi gine ringre joma otho mosepiem koda, kudni machamogi ok notho kata mach mawangʼogi ok notho kendo ginibed gik ma piny ngima ojokgo.”

< Isaiah 66 >