< Isaiah 66 >

1 Báyìí ni Olúwa wí: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà? Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
Mao kini ang giingon ni Jehova: Ang langit mao ang akong trono, ug ang yuta mao ang akong tumbanan: unsang dagwaya sa balay nga inyong pagatukoron alang kanako? ug unsang dapita ang akong pagapahulayan?
2 Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?” ni Olúwa wí. “Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí: ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀, tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
Kay kining tanan nga mga butanga gibuhat sa akong kamot, ug tungod niini kining tanan nga mga butanga nangamao, nag-ingon si Jehova: apan niining tawohana motan-aw ako, bisan pa kaniya nga kabus ug adunay espiritu nga mahinulsolon, ug nga nagapangurog tungod sa akong pulong.
3 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ, dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá, ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí, dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà. Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n, ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn,
Kadtong nagapatay ug usa ka vaca nga toro sama da niadtong nagapatay sa usa ka tawo; kadtong nagahalad ug usa ka carnero nga nati, sama man niadtong nagalunggo sa liog sa usa ka iro; kadtong nagahalad ug halad-nga-kalan-on, sama man niadtong nagahalad ug dugo sa baboy; kadtong nagasunog ug incienso, sama man niadtong nagapanalangin sa usa ka dios-dios. Oo, gipili nila ang ilang kaugalingong mga dalan, ug ang ilang kalag nahimuot sa ilang kaugalingong mga dulumtanan:
4 fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn. Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀. Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”
Pagapilion ko usab ang ilang mga kasaypanan, ug pagadad-on ko ang ilang mga kahadlok sa ibabaw nila; tungod kay sa diha nga ako nagtawag, walay mitubag; sa diha nga ako misulti, sila wala mamati: apan gihimo nila ang dautan sa akong mga mata, ug gipili kadtong wala nako kahimut-i.
5 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín, tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé, ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo, kí a le rí ayọ̀ yín!’ Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
Patalinghugi ang pulong ni Jehova, kamo nga nanagpangurog sa iyang pulong: Ang inyong kaigsoonan nga nagadumot kaninyo, nga nagasalikway kaninyo tungod sa akong ngalan, nag-ingon: Ipapaghimaya si Jehova, aron makita namo ang inyong kalipay; apan sila mao ang pagapakaulawan.
6 Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá, gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá! Ariwo tí Olúwa ní í ṣe tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí wọn.
Ang tingog sa kagubot gikan sa ciudad, ang tingog nga gikan sa templo, ang tingog ni Jehova nga nagahatag ug balus sa iyang mga kaaway.
7 “Kí ó tó lọ sí ìrọbí, ó ti bímọ; kí ó tó di pé ìrora dé bá a, ó ti bí ọmọkùnrin.
Sa wala pa siya pagsakiti, siya nanganak; sa wala pa siya sul-i, siya nanganak ug usa ka bata nga lalake.
8 Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan? Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
Kinsay nakadungog sa ingon nianang butanga? kinsay nakakita sa ingon nianang mga butanga? Matawo ba ang usa ka yuta sa usa ka adlaw? Mahimugso ba ang usa ka nasud sa diha-diha? kay sa gilayon nga ang Sion gisul-an, gianak niya ang iyang mga anak.
9 Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí kí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ nígbà tí mo ń mú ìbí wá?” Ni Ọlọ́run yín wí.
Magapakatawo ba ako sa mga kabataan, ug unya dili ko ipahimugso? miingon si Jehova: ako nga magapakatawo sa mga kabataan, motak-um ba sa tagoangkan? miingon ang imong Dios.
10 “Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀; ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
Managmaya kamo uban sa Jerusalem, ug managsadya alang kaniya, kamong tanan nga nahigugma kaniya: managmaya tungod sa kalipay uban kaniya, kamong tanan nga nanagbalata tungod kaniya;
11 Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára, ẹ̀yin yóò mu àmuyó ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”
Aron kamo makasuso ug mabusog tungod sa mga dughan sa iyang mga pagkalipay; aron kamo magapagatas, ug mahimuot sa kadagaya sa iyang himaya.
12 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi; ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀ a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
Kay mao kini ang giingon ni Jehova: Ania karon, ako mohatag ug pakigdait kaniya sama sa usa ka suba, ug ang himaya sa mga nasud sama sa usa ka suba nga nagaawas: ug kamo magasupsop niini; kamo pagasalapwangon sa mga hawak, ug pagayogyogon ibabaw sa mga tuhod.
13 Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”
Ingon sa usa ka bata nga ginalipay sa iyang inahan, mao man pagalipayon ko kamo; ug kamo pagalipayon diha sa Jerusalem.
14 Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko; ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Ug kamo makakita niini, ug ang inyong kasingkasing magakalipay, ug ang inyong mga bukog molambo sama sa lunhaw nga balili: ug ang kamot ni Jehova maila sa iyang mga alagad; ug siya masilag batok sa iyang mga kaaway.
15 Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle; òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú, àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
Kay, ania karon, si Jehova moanhi uban ang kalayo, ug ang iyang mga carro mahasama sa alimpulos; aron sa pagpahamtang sa iyang kasuko uban ang kabangis, ug sa iyang pagbadlong uban sa mga siga sa kalayo.
16 Nítorí pẹ̀lú iná àti idà ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.
Kay pinaagi sa kalayo si Jehova mopahamtang sa hukom, ug pinaagi sa iyang espada, ibabaw sa tanang unod; ug ang mga pinatay ni Jehova daghan.
17 “Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.
Kadtong nagabalaan sa ilang kaugalingon ug nagaputli sa ilang kaugalingon aron sa pag-adto sa mga tanaman, sa luyo sa usa diha sa taliwala, nagakaon ug unod sa baboy, ug ang dulumtanan, ug ang ilaga, silang tanan magadungan sa pagdangat sa katapusan, nag-ingon si Jehova.
18 “Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.
Kay ako nasayud sa ilang mga buhat ug sa ilang mga hunahuna: ang panahon moabut, nga pagatiponon ko ang tanan nga mga nasud ug mga dila; ug sila manganhi, ug makakita sa akong himaya.
19 “Èmi yóò sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Ug magabutang ako ug timaan sa taliwala nila, ug ako nga ipadala kadtong mga nangalagiw gikan kanila ngadto sa mga nasud, sa Tarsis, sa Pul, ug sa Lud, nga nagapamana, sa Tubal ug sa Javan, ngadto sa mga pulo nga halayo, nga wala makadungog sa akong kabantug, ni makakita sa akong himaya; ug sila magapahayag sa akong himaya sa taliwala sa mga nasud.
20 Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ̀-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́.
Ug ila nga dad-on ang tanan ninyo nga mga kaigsoonan gikan sa tanan nga mga nasud alang sa usa ka halad ngadto kang Jehova, sa ibabaw sa mga kabayo, ug sa sulod sa mga carro, ug sa mga talabon, ug sa ibabaw sa mga mula, ug sa ibabaw sa mga camello, ngadto sa akong balaan nga bukid nga Jerusalem, nag-ingon si Jehova, sa diha nga ang mga anak sa Israel maghatud sa ilang halad sa usa ka malinis nga sudlanan ngadto sa balay ni Jehova.
21 Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.
Ug gikan kanila usab ako mokuha aron himoon nga mga sacerdote ug aron himoon nga mga Levihanon, miingon si Jehova.
22 “Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé.
Kay ingon nga ang bag-ong mga langit ug ang bag-o nga yuta, nga akong pagabuhaton, magapabilin sa akong atubangan, miingon si Jehova, mao man magapabilin ang inyong kaliwatan ug ang inyong ngalan.
23 Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí.
Ug mahanabo, nga gikan sa bag-ong pagsubang sa bulan hangtud sa usa, ug gikan sa usa ka adlawng igpapahulay hangtud sa usa, ang tanang mga katawohan manganhi aron sa pagsimba sa akong atubangan, miingon si Jehova.
24 “Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”
Ug sila manggula, ug manan-aw sa mga minatay sa mga tawo nga nanaglapas batok kanako: kay ang ilang ulod dili mamatay, ni mapalong ang ilang kalayo; ug sila mahimong usa ka dulumtanan sa tanang mga unod.

< Isaiah 66 >