< Isaiah 65 >

1 “Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi; àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi. Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi, ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’
Je me suis fait rechercher de ceux qui ne me demandaient point, et je me suis fait trouver à ceux qui ne me cherchaient point; j'ai dit à la nation qui ne s'appelait point de mon Nom; me voici, me voici.
2 Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle, tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára, tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn
J'ai tout le jour étendu mes mains au peuple rebelle, à ceux qui marchent dans le mauvais chemin, [savoir] après leurs pensées;
3 àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo lójú ara mi gan an, wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;
Au peuple de ceux qui m'irritent continuellement en face, qui sacrifient dans les jardins, et qui font des parfums sur les [autels de] briques.
4 wọ́n ń jókòó láàrín ibojì wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀; tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀, tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;
Qui se tiennent dans les sépulcres, et passent la nuit dans les lieux désolés; qui mangent la chair de pourceau, et qui [ont dans] leurs vaisseaux le jus des choses abominables.
5 tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’ Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.
Qui disent; retire toi, n'approche point de moi, car je suis plus saint que toi; ceux-là sont une fumée à mes narines, un feu ardent tout le jour.
6 “Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi, Èmi kì yóò dákẹ́, ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́; Èmi yóò san án padà sí àyà wọn
Voici, ceci est écrit devant moi, je ne m'en tairai point, mais je le rendrai, oui je le rendrai dans leur sein,
7 àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,” ni Olúwa wí. “Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré, Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”
[A savoir] vos iniquités, et les iniquités de vos pères ensemble, a dit l'Eternel; lesquels ont fait des parfums sur les montagnes, et m'ont déshonoré sur les coteaux; c'est pourquoi je leur mesurerai aussi dans leur sein le salaire de ce qu'ils ont fait au commencement.
8 Báyìí ni Olúwa wí: “Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘Má ṣe bà á jẹ́, nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’ bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi; Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.
Ainsi a dit l'Eternel; comme quand on trouve dans une grappe du vin [à épreindre], et qu'on dit; ne la gâte pas, car il y a en elle de la bénédiction; j'en ferai de même à cause de mes serviteurs, afin que le tout ne soit point détruit.
9 Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu, àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì; àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn, ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.
Et je ferai sortir de la postérité de Jacob et de Juda celui qui héritera mes montagnes, et mes élus hériteront le pays, et mes serviteurs y habiteront.
10 Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran, àti àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran, fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.
Et Saron sera pour les cabanes du menu bétail, et la vallée de Hachor sera le gîte du gros bétail, pour mon peuple qui m'aura recherché.
11 “Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi, tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,
Mais vous, qui abandonnez l'Eternel, et qui oubliez la montagne de ma sainteté, qui dressez la table à l'armée des cieux, et qui fournissez l'aspersion à autant qu'on en peut compter;
12 Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà, àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa; nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn. Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀. Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”
Je vous compterai aussi avec l'épée, et vous serez tous courbés, pour être égorgés; parce que j'ai appelé, et que vous n'avez point répondu; j'ai parlé, et vous n'avez point écouté; mais vous avez fait ce qui me déplaît, et vous avez choisi les choses auxquelles je ne prends point de plaisir.
13 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun; ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin, àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu, ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin; àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀, ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.
C'est pourquoi, ainsi a dit le Seigneur l'Eternel; voici, mes serviteurs mangeront, et vous aurez faim; voici, mes serviteurs boiront, et vous aurez soif; voici mes serviteurs se réjouiront, et vous serez honteux.
14 Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè láti inú ìrora ọkàn yín àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.
Voici, mes serviteurs se réjouiront avec chant de triomphe pour la joie qu'ils auront au cœur, mais vous crierez pour la douleur que vous aurez au cœur, et vous hurlerez à cause de l'accablement de votre esprit.
15 Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀ fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún; Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín, ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun yóò fún ní orúkọ mìíràn.
Et vous laisserez votre nom à mes élus pour s'en servir dans les exécrations, et le Seigneur l'Eternel te fera mourir; mais il appellera ses serviteurs d'un autre nom.
16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́; Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́. Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.
Celui qui se bénira en la terre, se bénira par le Dieu de Vérité; et celui qui jurera sur la terre, jurera par le Dieu de Vérité; car les angoisses du passé seront oubliées, et même elles seront cachées devant mes yeux.
17 “Kíyèsi i, Èmi yóò dá àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun. A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́, tàbí kí wọn wá sí ọkàn.
Car voici, je m'en vais créer de nouveaux cieux, et une nouvelle terre; et on ne se souviendra plus des choses précédentes, et elles ne reviendront plus au cœur.
18 Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé nínú ohun tí èmi yóò dá, nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.
Mais plutôt vous vous réjouirez, et vous vous égayerez à toujours en ce que je m'en vais créer; car voici, je m'en vais créer Jérusalem, pour n'être que joie, et son peuple, pour n'être qu'allégresse.
19 Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi; ariwo ẹkún àti igbe ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.
Je m'égayerai donc sur Jérusalem, et je me réjouirai sur mon peuple; et on n'y entendra plus de voix de pleurs, ni de voix de clameurs.
20 “Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀, tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán; ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé; ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan ni a ó pè ní ẹni ìfibú.
Il n'y aura plus désormais aucun enfant né depuis peu de jours, ni aucun vieillard qui n'accomplisse ses jours; car celui qui mourra âgé de cent ans [sera encore] jeune; mais le pécheur âgé de cent ans sera maudit.
21 Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.
Même ils bâtiront des maisons, et y habiteront; ils planteront des vignes, et ils en mangeront le fruit.
22 Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé, tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ. Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan, bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí; àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́ wọn fún ìgbà pípẹ́.
Ils ne bâtiront pas des maisons afin qu'un autre y habite; ils ne planteront pas [des vignes] afin qu'un autre en mange le fruit; car les jours de mon peuple seront comme les jours des arbres; et mes élus perpétueront le travail de leurs mains.
23 Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán, wọn kí yóò bímọ fún wàhálà; nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún, àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.
Ils ne travailleront plus en vain, et n'engendreront [plus des enfants pour être exposés] à la frayeur; car ils seront la postérité des bénis de l'Eternel, et ceux qui sortiront d'eux seront avec eux.
24 Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn; nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.
Et il arrivera qu'avant qu'ils crient, je les exaucerai; et lorsque encore ils parleront, je les aurai [déjà] ouïs.
25 Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀, kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù, ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò. Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi,” ni Olúwa wí.
Le loup et l'agneau paîtront ensemble, et le lion mangera du fourrage comme le bœuf, et la poudre sera la nourriture du serpent; on ne nuira point, et on ne fera aucun dommage dans toute la montagne de ma sainteté; a dit l'Eternel.

< Isaiah 65 >