< Isaiah 65 >

1 “Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi; àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi. Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi, ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’
Kai khae hni vai ai kaminawk khaeah kang phong pae moe, kai pakrong ai kaminawk mah ang hnuk o boeh; ka hmin hoi kawk vai ai ih prae kami khaeah, Kai hae na khen oh, na khen oh, tiah ka naa.
2 Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle, tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára, tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn
A poek o haih palungthin baktih toengah, sethaih loklam pazui kaminawk, lokaek thaih kaminawk nuiah athun qui ban ka payangh thuih,
3 àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo lójú ara mi gan an, wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;
to baktih kaminawk loe takha thungah hmuen tathlanghaih to sak o moe, boeng ai ah kai palungphuisak hanah ka hmaa ah, thlung hoi sak ih hmaicam nuiah moi angbawnhaih to a sak o;
4 wọ́n ń jókòó láàrín ibojì wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀; tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀, tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;
nihcae loe taprong ah anghnut o moe, taprong ah iih o; okmoi to caak o moe, panuet thok moitui to laom thungah suek o,
5 tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’ Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.
nihcae mah, Kamhoe ah angdoe ah, ka taengah anghnai hmah; kai loe nang pongah ka ciim kue, tiah thuih o. To baktih kaminawk loe ka hnah hanah hmaikhue ah oh o moe, athun qui angqong hmai baktiah oh o.
6 “Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi, Èmi kì yóò dákẹ́, ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́; Èmi yóò san án padà sí àyà wọn
Khenah, ka hmaa ah tarik boeh pongah, ka om duem mak ai; sak ih atho ka pathok let han; nihcae ih saoek nuiah sakhaih atho ka pathok pae han,
7 àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,” ni Olúwa wí. “Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré, Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”
nangcae zaehaih hoi nam panawk zaehaih to ka pathok boih let han; nihcae loe mae nuiah hmuihoih tui to thlaek o moe, maesomnawk nuiah ka hmin to panuet kaom ah sak o pongah, canghnii ah a sak o ih hmuennawk to nihcae ih saoek nuiah ka tah pae han, tiah Angraeng mah thuih.
8 Báyìí ni Olúwa wí: “Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘Má ṣe bà á jẹ́, nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’ bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi; Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.
Angraeng mah hae tiah thuih; Misurtui suekhaih tabu thungah misurtui oh vop pongah, amrosak hmah, tahamhoihaih a thungah oh vop, tiah minawk mah thuih o baktih toengah, ka tamnanawk pongah, to kaminawk to kam rosak boih mak ai.
9 Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu, àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì; àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn, ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.
Jakob thung hoiah caanawk to ka tacawtsak moe, Judah thung hoiah kai ih mae qawktoep kami to ka tacawtsak han; ka qoih ih kaminawk mah maenawk to toep o ueloe, ka tamnanawk loe to ah om o tih.
10 Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran, àti àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran, fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.
Sharon loe kai pakrong kaminawk hanah, tuu pacahhaih ahmuen ah om ueloe, Akhor azawn loe maitaw prathaih ahmuen ah om tih.
11 “Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi, tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,
Toe nangcae loe Angraeng pahnawt kami, Kai ih kaciim mae pahnet kami, Gad kaminawk ih sithaw khaeah caboi patoemh kami, Meni sithaw han angbawnhaih tui paek kami ah na oh o.
12 Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà, àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa; nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn. Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀. Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”
To pongah nangcae to ka kroek moe, sumsen khaeah kang paek o han, nangcae loe hum boih hanah nam tueng o sut tih; tipong ah tih nahaeloe kang kawk o naah nang pathim o ai, lok kang thuih o naah na tahngai o ai; ka hmaa ah kasae hmuen na sak o moe, ka koeh ai ih hmuen to na qoih o.
13 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun; ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin, àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu, ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin; àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀, ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.
To pongah Angraeng Sithaw mah hae tiah thuih; Khenah, ka tamnanawk loe caa o tih, toe nangcae loe zok amthlam ah na om o tih; khenah, ka tamnanawk loe nae o tih, toe nangcae loe tui anghae ah na om o tih; khenah, ka tamnanawk loe anghoe o tih, toe nangcae loe azathaih hoiah na om o tih.
14 Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè láti inú ìrora ọkàn yín àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.
Khenah, ka tamnanawk loe palung anghoehaih hoiah laa to sah o tih, toe nangcae loe poek patangkhanghaih hoiah na qah o tih, palungboeng loiah na hang o tih.
15 Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀ fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún; Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín, ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun yóò fún ní orúkọ mìíràn.
Ka qoih ih kaminawk khaeah na hmin tangoeng hanah na caeh o taak sut tih; Angraeng Sithaw mah nangcae to hum tih, toe a tamnanawk loe ahmin kalah hoiah kawk tih.
16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́; Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́. Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.
Canghnii ih raihaihnawk to pahnet boeh moe, ka hmaa hoiah anghmat o boih boeh pongah, long nuiah angmah hoi angmah tahamhoihaih paek kami loe loktang Sithaw rang hoiah tahamhoihaih to paek tih; long ah lokkamhaih sah kami loe loktang Sithaw rang hoiah lokkamhaih to sah tih.
17 “Kíyèsi i, Èmi yóò dá àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun. A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́, tàbí kí wọn wá sí ọkàn.
Khenah, van kangtha hoi long kangtha to ka sak; hmaloe ih hmuennawk loe poek let mak ai boeh, palung thungah doeh om mak ai boeh.
18 Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé nínú ohun tí èmi yóò dá, nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.
Ka sak ih hmuen to oep oh loe, dungzan ah anghoe oh; khenah, Jerusalem loe anghoe moe, a thung ih kaminawk doeh anghoe o toeng hanah ka sak.
19 Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi; ariwo ẹkún àti igbe ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.
Jerusalem nuiah anghoehaih katawnh, kaimah ih kaminawk khaeah kang hoe han boeh; vangpui thungah qahhaih hoi hanghaih loknawk to thaih mak ai boeh.
20 “Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀, tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán; ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé; ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan ni a ó pè ní ẹni ìfibú.
To vangpui thungah loe nawkta om mak ai, saning koep ai mitong doeh om mak ai boeh; saning cumvaito naah dueh kami loe, nawkta nathuem ah dueh kami baktiah poek o tih; toe saning cumvaito hing ai ah dueh kami loe tangoenghaih tongh kami baktiah poek o tih.
21 Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.
Nihcae mah im to sah o ueloe, om o haih tih; misur takha to sah o ueloe, athaih to caa o tih.
22 Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé, tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ. Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan, bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí; àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́ wọn fún ìgbà pípẹ́.
A sak o ih im to minawk kalah mah om o haih mak ai, a thling o ih misur to minawk kalah mah caa pae o mak ai boeh; kai ih kaminawk hinghaih loe thing hinghaih baktiah om tih boeh; ka qoih ih kaminawk loe angmacae ban hoi sak ih hmuen to saning kasawkah caa o tih boeh.
23 Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán, wọn kí yóò bímọ fún wàhálà; nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún, àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.
Azom pui ah toksah kami om mak ai boeh, raihaih paek caanawk doeh tapen o mak ai boeh; angmacae hoi a caanawk loe, Angraeng tahamhoihaih hnu kami ah om o tih boeh.
24 Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn; nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.
Nihcae mah kawk ai naah, ka oi pae moe, lok a thuih o li naah, ka tahngaih pae han boeh.
25 Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀, kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù, ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò. Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi,” ni Olúwa wí.
Tasui hoi tuuca rawkcak nawnto caa hoi tih, kaipui loe maitaw tae baktiah caphaeh to caa tih boeh; toe maiphu loe pahui ih buh ah om tih. Kai ih kaciim mae boih ah loe maeto hoi maeto nganbawh kana paekhaih hoi amrohaih to om mak ai boeh, tiah Angraeng mah thuih.

< Isaiah 65 >