< Isaiah 64 >

1 Ìwọ ìbá fa ọ̀run ya kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá, tí àwọn òkè ńlá yóò fi wárìrì níwájú rẹ!
Obyś rozdarł niebiosa, i zstąpił, aby się od oblicza twego góry rozpłynęły!
2 Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí iná mú ẹ̀ka igi jó tí ó sì mú kí omi ó hó, sọ̀kalẹ̀ wá kí orúkọ rẹ le di mí mọ̀ fún àwọn ọ̀tá rẹ kí o sì jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó wárìrì níwájú rẹ!
(Jako od gorejącego ognia, ognia roztapiającego, woda wre, ) abyś oznajmił imię twoje nieprzyjaciołom twoim, ażeby się od oblicza twego narody zatrwożyły.
3 Nítorí nígbà tí o bá ṣe àwọn ohun ẹ̀rù tí àwa kò nírètí, o sọ̀kalẹ̀ wá, àwọn òkè ńlá sì wárìrì níwájú rẹ̀.
Jako gdyś czynił dziwy, którycheśmy się nie spodziewali; zstąpiłeś, a od oblicza twego góry się rozpływały.
4 Láti ìgbà àtijọ́ kò sí ẹni tí ó gbọ́ rí kò sí etí kan tí ó gbọ́ ọ, kò sí ojú tí ó tí ì rí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn rẹ, tí ó máa ń ṣe nǹkan lórúkọ àwọn tí ó dúró dè é.
Czego od wieków nie słyszano ani to do uszów przychodziło; oko nie widziało Boga innego oprócz ciebie, coby tak uczynił temu, co nań oczekuje.
5 Ìwọ a máa wá fún ìrànlọ́wọ́ àwọn tí wọn ń fi ayọ̀ ṣe ohun tó tọ́, tí ó rántí ọ̀nà rẹ. Ṣùgbọ́n nígbà tí a bẹ̀rẹ̀ sí dẹ́ṣẹ̀ sí wọn, inú bí ọ. Báwo ni a ó ṣe gbà wá là?
Zabieżałeś weselącemu się i czyniącemu sprawiedliwość, i tym, którzy na drogach twoich wspominali na cię. Otoś się ty rozgniewał, przeto żeśmy grzeszyli na tych drogach ustawicznie, wszakże zachowani będziemy,
6 Gbogbo wa ti dàbí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́, gbogbo òdodo wa sì dàbí èkísà ẹlẹ́gbin; gbogbo wa kákò bí ewé, àti bí afẹ́fẹ́, ẹ̀ṣẹ̀ wa ti gbá wa lọ kúrò.
Aczkolwiek jesteśmy jako nieczysty my wszyscy, i jako szata splugawiona są wszystkie sprawiedliwości nasze; przetoż wszyscy opadamy jako liść, a nieprawości nasze jako wiatr unoszą nas.
7 Ẹnikẹ́ni kò pe orúkọ rẹ tàbí kí ó gbìyànjú láti dì ẹ́ mú; nítorí ìwọ ti fi ojú rẹ pamọ́ fún wa ó sì jẹ́ kí àwa ṣòfò dànù nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.
Nadto niemasz, ktoby wzywał imienia twego, i pobudził się do tego, aby się chwycił ciebie, przynajmniej teraz, gdyś zakrył twarz swoję przed nami, a sprawiłeś, abyśmy niszczeli dla nieprawości naszych.
8 Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa, ìwọ ni Baba wa. Àwa ni amọ̀, ìwọ ni amọ̀kòkò; gbogbo wa jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Ale teraz, o Panie! tyś jest ojciec nasz, myśmy glina, a tyś twórca nasz; a takeśmy wszyscy dziełem ręki twojej.
9 Má ṣe bínú kọjá ààlà, ìwọ Olúwa, má ṣe rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa títí láé. Jọ̀wọ́, bojú wò wá, ni a gbàdúrà, nítorí ènìyàn rẹ ni gbogbo wa.
Nie gniewaj się, Panie! tak bardzo, a nie na wieki pomnij nieprawości naszej: oto wejrzyj proszę, myśmy wszyscy ludem twoim.
10 Àwọn ìlú mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀; Sioni pàápàá di aṣálẹ̀, Jerusalẹmu di ahoro.
Miasta świętobliwości twojej obrócone są w pustynię, Syon w pustynię, a Jeruzalem w spustoszenie obrócone.
11 Tẹmpili mímọ́ ológo wa, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́, ni a ti fi iná sun, àti ohun gbogbo tí í ṣe ìṣúra wa ti dahoro.
Dom świętobliwości naszej i ozdoby naszej, w którym cię chwalili ojcowie nasi, ogniem jest spalony, i wszystkie najkosztowniejsze rzeczy nasze obróciły się w pustki.
12 Lẹ́yìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí, Olúwa, ìwọ ó ha sì tún fi ara rẹ pamọ́ bí? Ìwọ ó ha dákẹ́ kí o sì fìyà jẹ wá kọjá ààlà bí?
Izali nad tem zatrzymasz się Panie? izali milczeć a nas tak bardzo trapić będziesz?

< Isaiah 64 >