< Isaiah 64 >

1 Ìwọ ìbá fa ọ̀run ya kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá, tí àwọn òkè ńlá yóò fi wárìrì níwájú rẹ!
Oh, vajha megszakasztanád az egeket és leszállnál, előtted a hegyek elolvadnának;
2 Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí iná mú ẹ̀ka igi jó tí ó sì mú kí omi ó hó, sọ̀kalẹ̀ wá kí orúkọ rẹ le di mí mọ̀ fún àwọn ọ̀tá rẹ kí o sì jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó wárìrì níwájú rẹ!
mint a tűz meggyújtja a rőzsét, a vizet a tűz felforralja; hogy nevedet ellenségidnek megjelentsd, hogy előtted reszkessenek a népek;
3 Nítorí nígbà tí o bá ṣe àwọn ohun ẹ̀rù tí àwa kò nírètí, o sọ̀kalẹ̀ wá, àwọn òkè ńlá sì wárìrì níwájú rẹ̀.
Hogy cselekednél rettenetes dolgokat, a miket nem vártunk; leszállnál és előtted a hegyek elolvadnának.
4 Láti ìgbà àtijọ́ kò sí ẹni tí ó gbọ́ rí kò sí etí kan tí ó gbọ́ ọ, kò sí ojú tí ó tí ì rí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn rẹ, tí ó máa ń ṣe nǹkan lórúkọ àwọn tí ó dúró dè é.
Hiszen öröktől fogva nem hallottak és fülökbe sem jutott, szem nem látott más Istent te kívüled, a ki így cselekszik azzal, a ki Őt várja.
5 Ìwọ a máa wá fún ìrànlọ́wọ́ àwọn tí wọn ń fi ayọ̀ ṣe ohun tó tọ́, tí ó rántí ọ̀nà rẹ. Ṣùgbọ́n nígbà tí a bẹ̀rẹ̀ sí dẹ́ṣẹ̀ sí wọn, inú bí ọ. Báwo ni a ó ṣe gbà wá là?
Elébe mégy annak, a ki örvend és igazságot cselekszik, a kik útaidban rólad emlékeznek! Ímé, Te felgerjedtél, és mi vétkezénk; régóta így vagyunk; megtartatunk-é?
6 Gbogbo wa ti dàbí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́, gbogbo òdodo wa sì dàbí èkísà ẹlẹ́gbin; gbogbo wa kákò bí ewé, àti bí afẹ́fẹ́, ẹ̀ṣẹ̀ wa ti gbá wa lọ kúrò.
És mi mindnyájan olyanok voltunk, mint a tisztátalan, és mint megfertéztetett ruha minden mi igazságaink, és elhervadánk, mint a falomb mindnyájan, és álnokságaink, mint a szél, hordának el bennünket!
7 Ẹnikẹ́ni kò pe orúkọ rẹ tàbí kí ó gbìyànjú láti dì ẹ́ mú; nítorí ìwọ ti fi ojú rẹ pamọ́ fún wa ó sì jẹ́ kí àwa ṣòfò dànù nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.
S nem volt, a ki segítségül hívta volna nevedet, a ki felserkenne és beléd fogóznék, mert orczádat elrejtéd tőlünk, és álnokságainkban minket megolvasztál.
8 Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa, ìwọ ni Baba wa. Àwa ni amọ̀, ìwọ ni amọ̀kòkò; gbogbo wa jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Most pedig, Uram, Atyánk vagy Te, mi sár vagyunk és Te a mi alkotónk, és kezed munkája vagyunk mi mindnyájan.
9 Má ṣe bínú kọjá ààlà, ìwọ Olúwa, má ṣe rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa títí láé. Jọ̀wọ́, bojú wò wá, ni a gbàdúrà, nítorí ènìyàn rẹ ni gbogbo wa.
Oh ne haragudjál Uram felettébb, és ne mindörökké emlékezzél meg álnokságinkról; ímé lásd, kérünk, mindnyájan a Te néped vagyunk.
10 Àwọn ìlú mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀; Sioni pàápàá di aṣálẹ̀, Jerusalẹmu di ahoro.
Szentségednek városai pusztává lettenek, Sion pusztává lőn, Jeruzsálem kietlenné.
11 Tẹmpili mímọ́ ológo wa, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́, ni a ti fi iná sun, àti ohun gbogbo tí í ṣe ìṣúra wa ti dahoro.
Szentségünk és ékességünk házát, hol téged atyáink dicsértenek, tűz perzselé föl, és minden a miben gyönyörködénk, elpusztult.
12 Lẹ́yìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí, Olúwa, ìwọ ó ha sì tún fi ara rẹ pamọ́ bí? Ìwọ ó ha dákẹ́ kí o sì fìyà jẹ wá kọjá ààlà bí?
Hát megtartóztatod-é magad mind e mellett is, Uram; hallgatsz-é és gyötörsz minket felettébb?

< Isaiah 64 >