< Isaiah 63 >

1 Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá, ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá? Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀, tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀? “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo tí ó ní ipa láti gbàlà.”
Cine este acesta care vine din Edom, cu veşminte vopsite din Boţra? Acesta care este glorios în haina lui, călătorind în măreţia tăriei lui? Eu cel ce vorbesc în dreptate, puternic pentru a salva.
2 Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?
Pentru ce îţi este haina roşie şi veşmintele tale ca cel ce calcă în teasc?
3 “Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì; láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi. Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi, mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Am călcat singur în teasc; şi din popor nu a fost nimeni cu mine, căci îi voi călca în mânia mea şi îi voi călca în picioare în furia mea; şi sângele lor va fi stropit pe veşmintele mele şi îmi voi întina toate hainele.
4 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé.
Fiindcă ziua răzbunării este în inima mea şi anul răscumpăraţilor mei este aproape.
5 Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́. Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́; nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Şi am privit şi nu a fost nimeni să ajute; şi m-am minunat că nu a fost nimeni să susţină, de aceea braţul meu mi-a adus salvare; şi furia mea, ea m-a susţinut.
6 Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi; nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”
Şi voi călca poporul în mânia mea şi îi voi îmbăta în furia mea şi voi doborî tăria lor la pământ.
7 Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwa, ìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún, gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wa, bẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣe fún ilé Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.
Voi aminti despre bunătatea iubitoare a DOMNULUI şi laudele DOMNULUI, conform cu tot ce a aşezat DOMNUL peste noi şi marea bunătate către casa lui Israel, pe care el a aşezat-o asupra lor conform îndurărilor lui şi conform mulţimii bunătăţilor lui iubitoare.
8 Ó wí pé, “Lóòtítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n, àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”; bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.
Fiindcă el a spus: Cu siguranţă ei sunt poporul meu, copii ce nu vor minţi, astfel el a fost Salvatorul lor.
9 Nínú gbogbo ìpọ́njú wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́ àti angẹli tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là. Nínú ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà; ó gbé wọn sókè ó sì pọ̀n wọ́n ní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.
În toată nenorocirea lor el a fost nenorocit şi îngerul dinaintea feţei lui i-a salvat, în dragostea lui şi în mila lui i-a răscumpărat; şi i-a dus şi i-a purtat în toate zilele din vechime.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀ wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀tá wọn òun tìkára rẹ̀ sì bá wọn jà.
Dar ei s-au răzvrătit şi au chinuit Duhul său sfânt, de aceea s-a întors pentru a fi duşmanul lor şi a luptat împotriva lor.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì, àwọn ọjọ́ Mose àti àwọn ènìyàn rẹ̀ níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la Òkun já, pẹ̀lú olùṣọ́-àgùntàn agbo ẹran rẹ̀? Níbo ni ẹni náà wà tí ó rán Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrín wọn,
Atunci şi-a amintit zilele din vechime, de Moise şi poporul său, spunând: Unde este cel care i-a adus din mare cu păstorul turmei lui? Unde este cel care a pus Duhul său sfânt în el?
12 ta ni ó rán apá ògo ti agbára rẹ̀ láti wà ní apá ọ̀tún Mose, ta ni ó pín omi ní yà níwájú wọn, láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,
Care i-a condus prin dreapta lui Moise cu braţul său glorios, despărţind apa înaintea lor, pentru a-şi face un nume veşnic?
13 ta ni ó síwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já? Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọsẹ̀;
Care i-a condus prin adânc, ca pe un cal în pustiu, ca ei să nu se poticnească?
14 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko, a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa. Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yín láti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.
Ca o fiară ce coboară în vale, Duhul DOMNULUI l-a făcut să se odihnească, astfel ai condus pe poporul tău, pentru a-ţi face un nume glorios.
15 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí i láti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo. Níbo ni ìtara àti agbára rẹ wà? Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni a ti mú kúrò níwájú wa.
Uită-te în jos din cer şi priveşte din locuinţa sfinţeniei tale şi a gloriei tale, unde este zelul şi tăria ta, fiorul adâncurilor şi a îndurărilor tale către mine? Sunt ele împiedicate?
16 Ṣùgbọ́n ìwọ ni baba wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abrahamu kò mọ̀ wá tàbí Israẹli mọ ẹni tí à á ṣe; ìwọ, Olúwa ni Baba wa, Olùràpadà wa láti ìgbà n nì ni orúkọ rẹ.
Fără îndoială tu eşti tatăl nostru, deşi dacă Avraam nu știe despre noi şi Israel nu ne recunoaşte, tu, DOAMNE, eşti tatăl nostru, răscumpărătorul nostru; numele tău este din veşnicie.
17 Èéṣe Olúwa tí o fi jẹ́ kí a ṣáko kúrò ní ojú ọ̀nà rẹ tí o sì ṣé àyà wa le tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi bọ̀wọ̀ fún ọ? Padà nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ẹ̀yà tí ṣe ogún ìní rẹ.
DOAMNE, de ce ne-ai făcut să rătăcim de la căile tale şi ne-ai împietrit inima de la frica de tine? Întoarce, de dragul servitorului tău, triburile moştenirii tale.
18 Fún ìgbà díẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ fi gba ibi mímọ́ rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwọn ọ̀tá wa ti tẹ ibi mímọ́ rẹ mọ́lẹ̀.
Poporul sfinţeniei tale l-a stăpânit doar puţin timp, potrivnicii noştri au călcat sanctuarul tău.
19 Àwa jẹ́ tìrẹ láti ìgbà n nì; ṣùgbọ́n ìwọ kò tí ì jẹ ọba lé wọn lórí, a kò sì tí ì pè wọ́n mọ́ orúkọ rẹ.
Noi suntem ai tăi, niciodată nu ai condus peste ei; nu s-au numit după numele tău.

< Isaiah 63 >