< Isaiah 63 >
1 Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá, ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá? Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀, tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀? “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo tí ó ní ipa láti gbàlà.”
Kim jest ten, który przybywa z Edomu, w farbowanych szatach z Bosry? Ten wspaniały w swoich szatach, kroczący w swojej wielkiej mocy? To ja jestem, który mówię w sprawiedliwości, potężny w wybawieniu.
2 Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?
Dlaczego twoja odzież jest czerwona? A twoje szaty jak u tego, który tłoczy w prasie?
3 “Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì; láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi. Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi, mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Sam jeden tłoczyłem prasę i spośród ludu nie było ze mną nikogo. Tłoczyłem go w swoim gniewie i deptałem go w swojej zapalczywości, aż pryskała jego krew na moje szaty, poplamiłem całą swą odzież.
4 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé.
Dzień pomsty był bowiem w moim sercu, a rok moich odkupionych nadszedł.
5 Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́. Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́; nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Rozglądałem się, ale nie było pomocnika, zdumiałem się, że nikogo nie było, kto by mnie podparł. Dlatego moje ramię przyniosło mi zbawienie, a moja zapalczywość – ona mnie podparła.
6 Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi; nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”
Zdeptałem narody w swoim gniewie, upoiłem je w swojej zapalczywości i uderzyłem o ziemię ich mocarzy.
7 Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwa, ìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún, gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wa, bẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣe fún ilé Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.
Będę wspominać miłosierdzie PANA i chwałę PANA za wszystko, co nam PAN wyświadczył, i za wielką dobroć, którą okazał domowi Izraela według swego miłosierdzia i według swojej wielkiej łaskawości.
8 Ó wí pé, “Lóòtítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n, àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”; bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.
Powiedział bowiem: Na pewno są moim ludem, synami, którzy mi się nie sprzeniewierzą. I tak stał się ich Zbawicielem.
9 Nínú gbogbo ìpọ́njú wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́ àti angẹli tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là. Nínú ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà; ó gbé wọn sókè ó sì pọ̀n wọ́n ní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.
We wszelkim ich ucisku i on był uciśniony, a Anioł jego oblicza zbawił ich. W swojej miłości i litości on ich odkupił. Troszczył się o nich i nosił ich przez wszystkie dni wieków.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀ wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀tá wọn òun tìkára rẹ̀ sì bá wọn jà.
Ale oni się zbuntowali i zasmucili jego Świętego Ducha. Dlatego zamienił się w ich wroga i walczył przeciwko nim.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì, àwọn ọjọ́ Mose àti àwọn ènìyàn rẹ̀ níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la Òkun já, pẹ̀lú olùṣọ́-àgùntàn agbo ẹran rẹ̀? Níbo ni ẹni náà wà tí ó rán Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrín wọn,
Wówczas wspomniał dawne dni, Mojżesza i jego lud, mówiąc: Gdzież jest ten, który ich wyprowadził z morza, z pasterzem swojej trzody? Gdzież jest ten, który włożył w jego wnętrze swego Świętego Ducha?
12 ta ni ó rán apá ògo ti agbára rẹ̀ láti wà ní apá ọ̀tún Mose, ta ni ó pín omi ní yà níwájú wọn, láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,
Który prowadził ich prawicą Mojżesza dzięki swemu chwalebnemu ramieniu i rozdzielił wody przed nimi, aby uczynić sobie wieczne imię?
13 ta ni ó síwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já? Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọsẹ̀;
Który ich przeprowadził przez głębiny, jak konia na pustyni, tak że się nie potknęli?
14 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko, a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa. Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yín láti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.
Jak bydło schodzące w dolinę tak Duch PANA spokojnie ich prowadził. Tak prowadziłeś swój lud, aby uczynić sobie chwalebne imię.
15 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí i láti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo. Níbo ni ìtara àti agbára rẹ wà? Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni a ti mú kúrò níwájú wa.
Spójrz z nieba i popatrz z przybytku swojej świętości i chwały. Gdzie twoja gorliwość i twoja wielka siła? Gdzie poruszenie twoich uczuć i litości przede mną? Czy powstrzymałeś [je]?
16 Ṣùgbọ́n ìwọ ni baba wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abrahamu kò mọ̀ wá tàbí Israẹli mọ ẹni tí à á ṣe; ìwọ, Olúwa ni Baba wa, Olùràpadà wa láti ìgbà n nì ni orúkọ rẹ.
Przecież ty jesteś naszym ojcem, bo Abraham nas nie zna, a Izrael nas nie uznaje. Ty, PANIE, jesteś naszym ojcem, naszym Odkupicielem; twoje imię jest od wieków.
17 Èéṣe Olúwa tí o fi jẹ́ kí a ṣáko kúrò ní ojú ọ̀nà rẹ tí o sì ṣé àyà wa le tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi bọ̀wọ̀ fún ọ? Padà nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ẹ̀yà tí ṣe ogún ìní rẹ.
Czemu, PANIE, pozwoliłeś nam zboczyć z twoich dróg i zatwardziłeś nasze serce, abyśmy się ciebie nie bali? Odwróć się ze względu na twoje sługi, pokolenia twego dziedzictwa.
18 Fún ìgbà díẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ fi gba ibi mímọ́ rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwọn ọ̀tá wa ti tẹ ibi mímọ́ rẹ mọ́lẹ̀.
Lud posiadł [ją] na krótki [czas], nasi wrogowie zaś zdeptali twoją świątynię.
19 Àwa jẹ́ tìrẹ láti ìgbà n nì; ṣùgbọ́n ìwọ kò tí ì jẹ ọba lé wọn lórí, a kò sì tí ì pè wọ́n mọ́ orúkọ rẹ.
My jesteśmy twoi. Nad nimi nigdy nie panowałeś ani nie byli nazywani twoimi imieniem.