< Isaiah 63 >

1 Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá, ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá? Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀, tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀? “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo tí ó ní ipa láti gbàlà.”
Któż to jest, który idzie z Edom, w szatach ubroczonych we krwi z Bocra? Ten przyozdobiony szatą swoją, postępujący w wielkości mocy swojej? Jam jest, który mówię sprawiedliwość, dostateczny do wybawienia.
2 Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?
Przeczże jest czerwone odzienie twoje? a szaty twoje jako tego, który tłoczy w prasie?
3 “Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì; láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi. Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi, mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Prasę tłoczyłem Ja sam, a nikt z ludu nie był zemnę; Ja, mówię, tłoczyłem nieprzyjaciół w gniewie swym, i podeptałem ich w popędliwości mojej, aż pryskała krew mocarzów ich na szaty moje; a tak wszystko odzienie moje spluskałem.
4 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé.
Albowiem dzień pomsty był w sercu mojem, a rok odkupionych moich przyszedł.
5 Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́. Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́; nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Lecz gdym widział, że nie było pomocnika, ażem się zdumał, że nikogo nie było, coby mię podparł, przetoż mi wybawienie sprawiło ramię moje, a popędliwość moja, ta mię podparła.
6 Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi; nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”
I podeptałem narody w gniewie swym, a opoiłem je w zapalczywości mojej, i uderzyłem o ziemię mocarzy ich.
7 Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwa, ìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún, gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wa, bẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣe fún ilé Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.
Miłosierdzia Pańskie wspominać będę, i chwały Pańskie za wszystko, cokolwiek nam uczynił Pan, i hojność dóbr, które pokazał domowi Izraelskiemu według miłosierdzia swego, i według wielkich litości swoich.
8 Ó wí pé, “Lóòtítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n, àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”; bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.
Bo rzekł: Wżdyć są ludem moim, są synami, nie przeniewierzą mi się; przetoż był ich zbawicielem.
9 Nínú gbogbo ìpọ́njú wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́ àti angẹli tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là. Nínú ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà; ó gbé wọn sókè ó sì pọ̀n wọ́n ní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.
We wszelakiem uciśnieniu ich i on był uciśniony: ale Anioł oblicza jego wybawił ich. Z miłości swej, i z litości swojej on sam odkupił ich, piastował ich i nosił ich po wszystkie dni wieków.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀ wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀tá wọn òun tìkára rẹ̀ sì bá wọn jà.
Ale oni odpornymi byli, i zasmucali Ducha jego Świętego; dla tego obrócił się im w nieprzyjaciela, a sam walczył przeciwko nim.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì, àwọn ọjọ́ Mose àti àwọn ènìyàn rẹ̀ níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la Òkun já, pẹ̀lú olùṣọ́-àgùntàn agbo ẹran rẹ̀? Níbo ni ẹni náà wà tí ó rán Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrín wọn,
I wspominał sobie lud jego na dni starodawne, i na Mojżesza, mówiąc: Gdzież jest ten, który ich wywiódł z morza, z pasterzem trzody swojej? Gdzież jest ten, który położył w pośrodku jego Ducha swego Świętego?
12 ta ni ó rán apá ògo ti agbára rẹ̀ láti wà ní apá ọ̀tún Mose, ta ni ó pín omi ní yà níwájú wọn, láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,
Który ich wiódł po prawicy Mojżeszowej ramieniem wielmożności swojej? który rozdzielił wody przed nimi, aby sobie uczynił imię wieczne?
13 ta ni ó síwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já? Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọsẹ̀;
Który ich przeprowadził przez przepaści, jako konia po puszczy, a nie szwankowali?
14 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko, a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa. Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yín láti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.
Jako gdy bydlę na dół zstępuje: tak Duch Pański zwolna prowadził z nich każdego; takeś wiódł lud swój, abyś sobie uczynił imię sławne.
15 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí i láti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo. Níbo ni ìtara àti agbára rẹ wà? Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni a ti mú kúrò níwájú wa.
Spojrzyjże z nieba, a obacz z mieszkania świętobliwości twojej, i ozdoby twojej. Gdzież jest gorliwość twoja, i wielka siła twoja? Gdzie wzruszenie wnętrzności twoich, i litości twoich? Przedemnąż zawściągnione będą?
16 Ṣùgbọ́n ìwọ ni baba wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abrahamu kò mọ̀ wá tàbí Israẹli mọ ẹni tí à á ṣe; ìwọ, Olúwa ni Baba wa, Olùràpadà wa láti ìgbà n nì ni orúkọ rẹ.
Tyś zaiste ojciec nasz: bo Abraham nie wie o nas, a Izrael nie zna nas. Tyś, Panie! ojciec nasz, odkupiciel nasz; toć jest od wieku imię twoje.
17 Èéṣe Olúwa tí o fi jẹ́ kí a ṣáko kúrò ní ojú ọ̀nà rẹ tí o sì ṣé àyà wa le tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi bọ̀wọ̀ fún ọ? Padà nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ẹ̀yà tí ṣe ogún ìní rẹ.
Przeczżeś nam, Panie! dopuścił błądzić z dróg twoich? przeczżeś zatwardził serce nasze, abyśmy się ciebie nie bali? Nawróćże się dla sług twoich, dla pokolenia dziedzictwa twego.
18 Fún ìgbà díẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ fi gba ibi mímọ́ rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwọn ọ̀tá wa ti tẹ ibi mímọ́ rẹ mọ́lẹ̀.
Na mały czas posiadł ziemię lud świętobliwości twojej; nieprzyjaciele nasi podeptali świątnicę twoję.
19 Àwa jẹ́ tìrẹ láti ìgbà n nì; ṣùgbọ́n ìwọ kò tí ì jẹ ọba lé wọn lórí, a kò sì tí ì pè wọ́n mọ́ orúkọ rẹ.
Myśmy twoi od wieku, a nad tymi nigdyś nie panował, ani wzywano imienia twego nad nimi.

< Isaiah 63 >