< Isaiah 63 >
1 Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá, ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá? Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀, tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀? “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo tí ó ní ipa láti gbàlà.”
Кой е този, що иде от Едом, С очервени дрехи от Восора, Този славен в облеклото си, Който ходи във величието на силата си? Аз съм, Който говори с правда, Мощен да спасявам.
2 Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?
Защо е червено облеклото Ти. И дрехите Ти подобни на ония на човек, който тъпче в лин?
3 “Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì; láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi. Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi, mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Аз сам изтъпках лина, И от племената не бе с Мене ни един човек; Да! стъпках ги в гнева Си, И смазах ги в яростта Си, Тъй че кръвта ми попръска дрехите Ми, И изцапах цялото Си облекло.
4 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé.
Защото денят за въздаянието бе в сърцето Ми, И годината Ми за изкупване настана.
5 Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́. Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́; nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Аз разгледах, но нямаше кой да подкрепя; И зачудих се, че нямаше кой да подкрепя; Затова, Моята мишца Ми изработи спасение, И Моята ярост, тя Ме подкрепи.
6 Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi; nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”
Аз стъпках племената в гнева Си, Опитах ги с яростта Си, И излях кръвта им на земята.
7 Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwa, ìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún, gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wa, bẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣe fún ilé Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.
Ще спомена милосърдията Господни, Причините за хвалене Господа За всичко, що ни е подарил Господ, И за голямата благост към Израилевия дом, Която им показа според щедростта Си, И според премногото Си милости.
8 Ó wí pé, “Lóòtítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n, àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”; bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.
Защото рече: Наистина те са Мои люде, Чада, които не ще постъпят невярно; Така им стана Спасител.
9 Nínú gbogbo ìpọ́njú wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́ àti angẹli tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là. Nínú ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà; ó gbé wọn sókè ó sì pọ̀n wọ́n ní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.
Във всичките им скърби Той скърбеше, И ангелът на присъствието Му ги избави; Поради любовта Си и поради милосърдието Си Той сам ги изкупи, Дигна ги и носи ги през всичките древни дни.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀ wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀tá wọn òun tìkára rẹ̀ sì bá wọn jà.
Но те се разбунтуваха и оскърбиха Светия Негов Дух; Затова Той се обърна та им стана неприятел, И сам воюва против тях.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì, àwọn ọjọ́ Mose àti àwọn ènìyàn rẹ̀ níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la Òkun já, pẹ̀lú olùṣọ́-àgùntàn agbo ẹran rẹ̀? Níbo ni ẹni náà wà tí ó rán Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrín wọn,
Тогава людете Му си спомниха за старите Моисееви времена, и казваха: Где е Оня, Който ги възведе от морето Чрез пастирите на стадото Си? - Где е оня, който положи Светия Си Дух всред тях?
12 ta ni ó rán apá ògo ti agbára rẹ̀ láti wà ní apá ọ̀tún Mose, ta ni ó pín omi ní yà níwájú wọn, láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,
Който направи славната Си мишца Да върви до Моисеевата десница? Който раздели водата пред тях, За да си придобие вечно име?
13 ta ni ó síwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já? Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọsẹ̀;
Който ги води през бездната, Както кон през пасбище, без да се препънат?
14 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko, a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa. Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yín láti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.
Духът Господен ги успокои Като добитък, който слиза в долината; Така си водил людете Си, За да си придобиеш славно име.
15 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí i láti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo. Níbo ni ìtara àti agbára rẹ wà? Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni a ti mú kúrò níwájú wa.
Погледни от небесата И виж от светото Си славно обиталище, Где са ревността Ти и могъществените Ти дела? Ожидането на Твоите милости и щедрости е въздържано спрямо мене.
16 Ṣùgbọ́n ìwọ ni baba wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abrahamu kò mọ̀ wá tàbí Israẹli mọ ẹni tí à á ṣe; ìwọ, Olúwa ni Baba wa, Olùràpadà wa láti ìgbà n nì ni orúkọ rẹ.
Защото Ти си наш Отец, Ако и да не ни знае Авраам И да не ни признае Израил; Ти, Господи, си наш Отец; Твоето име е наш вечен Изкупител.
17 Èéṣe Olúwa tí o fi jẹ́ kí a ṣáko kúrò ní ojú ọ̀nà rẹ tí o sì ṣé àyà wa le tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi bọ̀wọ̀ fún ọ? Padà nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ẹ̀yà tí ṣe ogún ìní rẹ.
Защо си допуснал, Господи, да се отклоняваме от пътищата Ти, Да ожесточаваме сърцата си та да не Ти се боим? Върни се заради слугите Си, Племената на Твоето наследство.
18 Fún ìgbà díẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ fi gba ibi mímọ́ rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwọn ọ̀tá wa ti tẹ ibi mímọ́ rẹ mọ́lẹ̀.
Малко време го владяха Твоите свети люде; Противниците ни потъпкаха светилището Ти.
19 Àwa jẹ́ tìrẹ láti ìgbà n nì; ṣùgbọ́n ìwọ kò tí ì jẹ ọba lé wọn lórí, a kò sì tí ì pè wọ́n mọ́ orúkọ rẹ.
Ние сме станали като ония, над които Ти никога не си владял, Като ония, които не са били наричани с името Ти.