< Isaiah 62 >
1 Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́, nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu, títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀, àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.
Ze względu na Syjon nie będę milczeć, ze względu na Jerozolimę nie spocznę, dopóki jego sprawiedliwość nie wzejdzie jak blask i jego zbawienie nie zapłonie jak pochodnia.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ, àti gbogbo ọba ògo rẹ a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.
I ujrzą narody twoją sprawiedliwość i wszyscy królowie – twoją chwałę. I nazwą cię nowym imieniem, które usta PANA ustalą.
3 Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa, adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.
I będziesz koroną chwały w ręku PANA i królewskim diademem w ręce twego Boga.
4 Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́ tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro. Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba, àti ilẹ̀ rẹ ní Beula; nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.
Nie będą cię więcej zwać Opuszczoną ani twoja ziemia nie będzie więcej nazwana Spustoszoną. Ale ty będziesz nazywana Chefsiba, a twoja ziemia Beula, bo PAN ma w tobie upodobanie i twoja ziemia będzie poślubiona.
5 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.
Jak bowiem młodzieniec poślubia dziewicę, tak twoi synowie cię poślubią. I jak oblubieniec raduje się z oblubienicy, tak twój Bóg będzie się radować z ciebie.
6 Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu; wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru. Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa, ẹ má ṣe fúnra yín ní ìsinmi,
Na twoich murach, Jerozolimo, postawiłem stróżów, którzy przez cały dzień i całą noc nigdy nie zamilkną. Wy, którzy wspominacie PANA, nie milczcie;
7 àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀ tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.
I nie dajcie mu odpoczynku, dopóki nie utwierdzi i dopóki nie uczyni Jerozolimy chwałą na ziemi.
8 Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti nípa agbára apá rẹ: “Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì tuntun rẹ mọ́ èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;
PAN przysiągł na swoją prawicę i na ramię swojej mocy: Nie wydam już twojej pszenicy na pokarm twoim wrogom, a synowie cudzoziemców nie będą pić twego wina, przy którym się trudziłaś.
9 ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́, tí wọn ó sì yin Olúwa, àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un, nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”
Ale ci, którzy je zgromadzą, będą je spożywać i chwalić PANA; a ci, którzy je zbierają, będą je pić w dziedzińcach mojej świątyni.
10 Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà! Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn. Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó! Ẹ ṣa òkúta kúrò. Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Przechodźcie, przechodźcie przez bramy! Torujcie drogę ludowi; wyrównajcie, wyrównajcie gościńce; usuwajcie kamienie, podnieście sztandar dla narodów.
11 Olúwa ti ṣe ìkéde títí dé òpin ilẹ̀ ayé: “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé, ‘Kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀! Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀, àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’”
Oto PAN rozkaże wołać aż po krańce ziemi: Powiedzcie córce Syjonu: Oto nadchodzi twój Zbawiciel, oto jego zapłata z nim, a jego dzieło przed nim.
12 A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́, ẹni ìràpadà Olúwa; a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri, ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.
Twoich synów nazwą Ludem Świętym, Odkupionymi PANA, a ciebie nazwą Poszukiwaną, Miastem Nieopuszczonym.