< Isaiah 62 >
1 Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́, nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu, títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀, àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.
Pour l'amour de Sion je ne me tiendrai point tranquille, et pour l'amour de Jérusalem je ne serai point en repos que sa justice ne sorte dehors comme une splendeur, et que sa délivrance ne soit allumée comme une lampe.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ, àti gbogbo ọba ògo rẹ a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.
Alors les nations verront ta justice, et tous les Rois, ta gloire; et on t'appellera d'un nouveau nom, que la bouche de l'Eternel aura expressément déclaré.
3 Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa, adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.
Tu seras une couronne d'ornement en la main de l'Eternel, et une tiare royale dans la main de ton Dieu.
4 Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́ tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro. Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba, àti ilẹ̀ rẹ ní Beula; nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.
On ne te nommera plus, la délaissée, et on ne nommera plus ta terre, la désolation; mais on t'appellera, mon bon plaisir en elle; et ta terre, la mariée, car l'Eternel prendra son bon plaisir en toi, et ta terre aura un mari.
5 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.
Car [comme] le jeune homme se marie à la vierge, [et comme] tes enfants se marient chez toi, ainsi ton Dieu se réjouira de toi, de la joie qu'un époux a de son épouse.
6 Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu; wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru. Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa, ẹ má ṣe fúnra yín ní ìsinmi,
Jérusalem, j'ai ordonné des gardes sur tes murailles tout le jour et toute la nuit continuellement, ils ne se tairont point. Vous qui faites mention de l'Eternel ne gardez point le silence.
7 àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀ tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.
Et ne discontinuez point de l'invoquer jusques à ce qu'il rétablisse et remette Jérusalem en un état renommé sur la terre.
8 Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti nípa agbára apá rẹ: “Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì tuntun rẹ mọ́ èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;
L'Eternel a juré par sa dextre, et par le bras de sa force; si je donne plus ton froment pour nourriture à tes ennemis, et si les étrangers boivent plus ton vin [excellent] pour lequel tu as travaillé.
9 ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́, tí wọn ó sì yin Olúwa, àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un, nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”
Car ceux qui auront amassé le froment, le mangeront, et ils loueront l'Eternel; et ceux qui auront recueilli [le vin], le boiront dans les parvis de ma sainteté.
10 Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà! Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn. Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó! Ẹ ṣa òkúta kúrò. Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Passez, passez par les portes, [disant]; Préparez le chemin du peuple, relevez, relevez le sentier, et ôtez-en les pierres, et élevez l'enseigne vers les peuples.
11 Olúwa ti ṣe ìkéde títí dé òpin ilẹ̀ ayé: “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé, ‘Kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀! Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀, àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’”
Voici, l'Eternel a fait entendre [ceci] jusques au bout de la terre; Dites à la fille de Sion; voici, ton Sauveur vient; voici, son salaire est par-devers lui, et sa récompense [marche] devant lui.
12 A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́, ẹni ìràpadà Olúwa; a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri, ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.
Et on les appellera, le peuple saint, les rachetés de l'Eternel, et on t'appellera, la recherchée, la ville non abandonnée.