< Isaiah 62 >

1 Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́, nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu, títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀, àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.
Because I am very concerned about [the people of] Jerusalem [DOU], I will do something to help them. I will not stop praying for them until they are rescued/freed [from their oppressors], until that becomes as apparent to everyone as the dawn [every morning], until people can see it as clearly as [SIM] they see a torch shining brightly [at night].
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ, àti gbogbo ọba ògo rẹ a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.
[Some day] the [people of many] nations will know that Yahweh has rescued you, [his people]. Their kings will see that your city is [very] great/glorious. And Yahweh [MTY] will give your [city] a new name.
3 Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa, adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.
[It will be as though] Yahweh will hold you up in his hands in order that everyone can see you. Under his authority [MTY], you will be [like] a glorious headband/turban worn by a king.
4 Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́ tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro. Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba, àti ilẹ̀ rẹ ní Beula; nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.
Your [city] will never again be called “the deserted/abandoned city” and your country will never again be called “the desolate land”; it will be called “the land that Yahweh delights in”, and [it will also be called] “married to Yahweh”. It will be called that because Yahweh will be delighted with you, [and it will be as though] you are his bride [MET].
5 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.
You people will live in all the country of Judah like [SIM] a young man lives with his bride. And our God will be happy that you [belong to] him like [SIM] a bridegroom is happy that his bride [belongs to him].
6 Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu; wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru. Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa, ẹ má ṣe fúnra yín ní ìsinmi,
[You people of] Jerusalem, I have placed watchmen on your walls; they will [LIT] earnestly pray to Yahweh day and night. You watchmen, you must not stop [praying] [and] reminding Yahweh [about what he has promised to do]!
7 àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀ tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.
And tell Yahweh that he should not rest until he causes Jerusalem to be [a city that is] famous throughout the world.
8 Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti nípa agbára apá rẹ: “Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì tuntun rẹ mọ́ èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;
Yahweh has raised his right hand to solemnly promise [to the people of Jerusalem], “I will use my power [MTY] and never again allow your enemies to defeat you; [soldiers from other nations will never come again] to take away your grain and the wine that you worked hard [to produce].
9 ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́, tí wọn ó sì yin Olúwa, àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un, nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”
You yourselves grew the grain, and you will be the ones who will praise [me], Yahweh, while you eat [the bread made from] that grain. Inside the courtyards of my temple you yourselves will drink the wine made from the grapes [that you harvested].”
10 Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà! Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn. Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó! Ẹ ṣa òkúta kúrò. Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Go out through the [city] gates! Prepare the highway on which people [will return from other countries]! Cause the road to become smooth; clear off [all] the stones; set up signal flags to help the people-groups to see [where the road to Jerusalem is].
11 Olúwa ti ṣe ìkéde títí dé òpin ilẹ̀ ayé: “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé, ‘Kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀! Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀, àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’”
This is the message that Yahweh has sent to [the people of] every nation: “Tell the people of Israel, ‘The one who will rescue/save you is coming! Look! He will be bringing to you (your reward/what you deserve [for the good things that you have done]); those whom he is setting free will be going ahead of him.’”
12 A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́, ẹni ìràpadà Olúwa; a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri, ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.
They will be called “Yahweh’s own people, the ones whom he rescued”. And Jerusalem will be known as the city that [Yahweh] loves, the city that is no [longer] abandoned.

< Isaiah 62 >