< Isaiah 62 >

1 Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́, nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu, títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀, àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.
Pro Sion nebudu mlčeti, a pro Jeruzalém neupokojím se, dokudž nevyjde jako blesk spravedlnost jeho, a spasení jeho jako pochodně hořeti nebude.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ, àti gbogbo ọba ògo rẹ a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.
I uzří národové spravedlnost tvou, a všickni králové slávu tvou, a nazovou tě jménem novým, kteréž ústa Hospodinova vyřknou.
3 Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa, adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.
Nadto budeš korunou ozdobnou v ruce Hospodinově, a korunou královskou v ruce Boha svého.
4 Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́ tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro. Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba, àti ilẹ̀ rẹ ní Beula; nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.
Nebudeš více slouti opuštěná, a země tvá nebude více slouti pustinou, ale ty nazývána budeš rozkoší, a země tvá vdanou; nebo rozkoš míti bude Hospodin v tobě, a země tvá bude vdaná.
5 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.
Nebo jakož pojímá mládenec pannu, tak tě sobě pojmou synové tvoji, a jakou má radost ženich z nevěsty, tak radovati se bude z tebe Bůh tvůj.
6 Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu; wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru. Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa, ẹ má ṣe fúnra yín ní ìsinmi,
Na zdech tvých, Jeruzaléme, postavím strážné, kteříž přes celý den i přes celou noc nikdy nebudou mlčeti. Kteříž tedy připomínáte Hospodina, nemlčtež,
7 àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀ tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.
A nedávejte jemu pokoje, dokudž neutvrdí, a dokudž nezpůsobí, aby Jeruzalém byl slavný na zemi.
8 Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti nípa agbára apá rẹ: “Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì tuntun rẹ mọ́ èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;
Přisáhltě Hospodin skrze pravici svou, a skrze rámě síly své, řka: Nikoli nedám obilí tvého více za pokrm nepřátelům tvým, aniž píti budou cizozemci vína tvého, o němž jsi pracoval.
9 ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́, tí wọn ó sì yin Olúwa, àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un, nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”
Ale ti, kteříž je shromažďují, budou je jísti, a chváliti Hospodina, a kteříž je zbírají, budou je píti v síňcích svatosti mé.
10 Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà! Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn. Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó! Ẹ ṣa òkúta kúrò. Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Vejdětež, vejdětež branami, spravte cestu lidu, vyrovnejte, vyrovnejte silnici, vybeřte kamení, vyzdvihněte korouhev k národům.
11 Olúwa ti ṣe ìkéde títí dé òpin ilẹ̀ ayé: “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé, ‘Kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀! Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀, àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’”
Aj, Hospodin rozkáže provolati až do končin země: Rcetež dceři Sionské: Aj, Spasitel tvůj béře se, aj, mzda jeho s ním, a dílo jeho před ním.
12 A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́, ẹni ìràpadà Olúwa; a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri, ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.
I nazovou syny tvé lidem svatým, vykoupenými Hospodinovými, ty pak slouti budeš městem vzácným a neopuštěným.

< Isaiah 62 >