< Isaiah 61 >

1 Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
Herrens, HERRENS Ande är över mig, ty HERREN har smort mig till att förkunna glädjens budskap för de ödmjuka; han har sänt mig till att läka dem som hava ett förkrossat hjärta, till att predika frihet för de fångna och förlossning för de bundna,
2 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
till att predika ett nådens år från HERREN och en hämndens dag från vår Gud, en dag, då han skall trösta alla sörjande,
3 àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
då han skall låta de sörjande i Sion få huvudprydnad i stället för aska, glädjeolja i stället för sorg, högtidskläder i stället för en bedrövad ande; och de skola kallas »rättfärdighetens terebinter», »HERRENS plantering, som han vill förhärliga sig med».
4 Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
Och de skola bygga upp de gamla ruinerna och upprätta förfädernas ödeplatser; de skola återställa de förödda städerna, de platser, som hava legat öde släkte efter släkte.
5 Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
Främlingar skola stå redo att föra edra hjordar i bet, och utlänningar skola bruka åt eder åkrar och vingårdar.
6 A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
Men I skolen heta HERRENS präster, och man skall kalla eder vår Guds tjänare; I skolen få njuta av folkens skatter, och deras härlighet skall övergå till eder.
7 Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
För eder skam skolen I få dubbelt igen, och de som ledo smälek skola nu jubla över sin del. Så skola de få dubbelt att besitta i sitt land; evig glädje skola de undfå.
8 “Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
Ty jag, HERREN, älskar, vad rätt är, och hatar orättfärdigt rov; och jag skall giva dem deras lön i trofasthet och sluta ett evigt förbund med dem.
9 A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
Och deras släkte skall bliva känt bland folken och deras avkomma bland folkslagen; alla som se dem skola märka på dem, att de äro ett släkte, som HERREN har välsignat.
10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
Jag gläder mig storligen i HERREN, och min själ fröjdar sig i min Gud, ty han har iklätt mig frälsningens klädnad och höljt mig i rättfärdighetens mantel, likasom när en brudgum sätter högtidsbindeln på sitt huvud eller likasom när en brud pryder sig med sina smycken.
11 Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.
Ty likasom jorden låter sina växter spira fram och en trädgård sin sådd växa upp, så skall Herren, HERREN låta rättfärdighet uppväxa och lovsång inför alla folk.

< Isaiah 61 >