< Isaiah 61 >

1 Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
Duhul Domnului DUMNEZEU este peste mine, deoarece DOMNUL m-a uns să predic veşti bune celor blânzi; el m-a trimis să leg pe cei cu inima zdrobită, să vestesc libertate captivilor şi deschiderea închisorii celor ce sunt legaţi.
2 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
Să vestesc anul de îndurare al DOMNULUI şi ziua răzbunării Dumnezeului nostru; să mângâi pe toţi cei care jelesc.
3 àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
Să rânduiesc celor ce jelesc în Sion, să le dau frumuseţe în locul cenuşii, untdelemnul bucuriei în locul jelirii, îmbrăcămintea de laudă în locul duhului de apăsare; să fie numiţi pomi ai dreptăţii, sadul DOMNULUI, ca el să fie glorificat.
4 Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
Iar ei vor rezidi vechile ruine, vor ridica din nou pustiirile de altădată şi vor repara cetăţile risipite, pustiirile multor generaţii.
5 Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
Şi străini vor sta şi vor paşte turmele tale şi fiii celor străini vor fi plugarii voştri şi vierii voştri.
6 A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
Dar voi veţi fi numiţi Preoţi ai DOMNULUI, oamenii vă vor numi Servitori ai Dumnezeului nostru, veţi mânca bogăţiile neamurilor şi în gloria lor vă veţi făli.
7 Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
În locul ruşinii voastre veţi primi dublu; şi în locul ocării se vor bucura în partea lor, de aceea în ţara lor ei vor stăpâni o parte dublă, bucurie veşnică vor avea.
8 “Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
Fiindcă eu, DOMNUL, iubesc judecata, urăsc jaful pentru ofranda arsă; şi voi conduce lucrarea lor în adevăr şi voi face un legământ veşnic cu ei.
9 A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
Şi sămânţa lor va fi cunoscută printre neamuri şi urmaşii lor printre popoare, toţi cei ce îi văd îi vor recunoaşte, că ei sunt sămânţa pe care DOMNUL a binecuvântat-o.
10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
Mă voi bucura mult în DOMNUL, sufletul meu se va veseli în Dumnezeul meu; căci m-a îmbrăcat cu veşmintele salvării, m-a acoperit cu roba dreptăţii, ca un mire ce se împodobeşte cu ornamente şi ca o mireasă ce se înfrumuseţează cu bijuterii.
11 Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.
Căci precum pământul aduce mugurul său şi precum grădina face lucrurile ce sunt semănate în ea să răsară, astfel Domnul DUMNEZEU va face dreptatea şi lauda să răsară înaintea tuturor naţiunilor.

< Isaiah 61 >