< Isaiah 61 >

1 Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
Duch Pana BOGA jest nade mną, bo PAN mnie namaścił, abym głosił dobrą nowinę cichym, posłał mnie, abym opatrzył rany skruszonym w sercu, abym zwiastował uwięzionym wyzwolenie, a związanym otworzenie więzienia;
2 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
Abym ogłosił miłościwy rok PANA i dzień pomsty naszego Boga; abym pocieszył wszystkich płaczących;
3 àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
Abym sprawił radość płaczącym w Syjonie i dał im ozdobę zamiast popiołu, olejek radości zamiast smutku, szatę chwały zamiast ducha przygnębienia; i będą nazwani drzewami sprawiedliwości, szczepem PANA, aby był uwielbiony.
4 Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
I odbudują starodawne ruiny, naprawią dawne spustoszenia i odnowią zniszczone miasta, opustoszałe od wielu pokoleń.
5 Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
I stawią się cudzoziemcy, i będą paść wasze stada, a synowie cudzoziemców będą waszymi oraczami i winogrodnikami.
6 A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
Ale wy będziecie nazwani kapłanami PANA, będą was nazywać sługami naszego Boga. Będziecie korzystać z bogactwa narodów i będziecie się chlubić ich chwałą.
7 Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
Za waszą hańbę [wynagrodzę] wam podwójnie, a zamiast wstydzić się, będziecie śpiewać; dlatego posiądziecie podwójne dziedzictwo z ich działu i w ich ziemi. I będziecie mieć wieczną radość.
8 “Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
Ja bowiem, PAN, miłuję sąd i nienawidzę grabieży dla całopalenia; dlatego sprawię, by wykonali swoje dzieła w prawdzie i zawrę z nimi wieczne przymierze.
9 A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
Ich potomstwo będzie znane wśród pogan, a ich potomkowie pośród ludów; wszyscy, którzy ich zobaczą, poznają, że są potomstwem błogosławionym przez PANA.
10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
Będę się wielce radować w PANU i moja dusza rozraduje się w moim Bogu, bo przyoblekł mnie w szaty zbawienia i przyodział mnie w płaszcz sprawiedliwości, jak przyozdobionego oblubieńca i jak oblubienicę ozdobioną swoimi klejnotami.
11 Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.
Jak ziemia bowiem wydaje swe plony i jak ogród wydaje nasienie, tak Pan BÓG sprawi, że wzejdzie sprawiedliwość i chwała przed wszystkimi narodami.

< Isaiah 61 >