< Isaiah 60 >

1 “Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
У ставай, світися, Єрусалиме, бо прийшло твоє світло, а слава Господня над тобою зася́ла!
2 Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́ ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
Бо те́мрява землю вкрива́є, а мо́рок — наро́ди, та сяє Господь над тобою, і слава Його над тобою з'явля́ється!
3 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ, àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.
І пі́дуть наро́ди за світлом твоїм, а царі — за ясністю ся́йва твого́.
4 “Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò. Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
Здійми́ свої очі навко́ло й побач: усі вони зі́брані, і до тебе ідуть; сини твої йдуть іздале́ка, а до́чок твоїх на рука́х он несуть!
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán, ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀; ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ, sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
Побачиш тоді — і роз'я́снишся ти, сполохне́ться й поши́ршає серце твоє, бо зве́рнеться мо́рське бага́тство до тебе, і при́йде до тебе багатство наро́дів!
6 Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani. Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá, wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́ tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
Бе́зліч верблю́дів закриє тебе, молоді ті верблю́ди з Мідія́ну й Ефи́, — усі вони при́йдуть із Ше́ви, носитимуть золото й ла́дан та хва́ли Господні звіща́тимуть.
7 Gbogbo agbo ẹran ìlú Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ, àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́; wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi, bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.
Всі отари кеда́рські зберу́ться до тебе, барани́ невайо́тські послу́жать тобі, — вони пі́дуть усі на Мій ві́втар, як жертва приє́мна, і Я просла́влю дім слави Своєї!
8 “Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru, gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
Хто вони, що летять, як та хмара, і немов голуби́ до своїх голубникі́в?
9 Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí; ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn, pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn, fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.
Бо до Мене збираються морепла́вці, і найперше пливуть кораблі́ із Тарші́шу, щоб приве́сти синів твоїх зда́лека, з ними їхнє срібло́ та їхнє золото для Імені Господа, Бога твого, і для Святого Ізраїля, Він бо просла́вив тебе.
10 “Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́, ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
І мури твої побуду́ють чужи́нці, а їхні царі́ тобі бу́дуть служи́ти, бо в за́палі гніву Свого́ Я був ура́зив тебе, а в Своїм уподо́банні змилуюся над тобою!
11 Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀, a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
І будуть пості́йно відкри́тими брами твої, — ані вдень, ні вночі не замкну́ться вони, щоб прино́сити до тебе бага́тство наро́дів, і їхні царі́ щоб були припрова́джені.
12 Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun; pátápátá ni yóò sì dahoro.
Бо погинуть наро́д та те ца́рство, що не схо́чуть служити тобі, — і ці наро́ди пони́щені будуть зовсі́м!
13 “Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀, láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi; àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
Слава ліва́нська прибу́де до тебе, кипари́с, сосна й бук будуть ра́зом, щоб приоздобити місце святині Моєї, і місце ніг Своїх Я пошану́ю.
14 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò wá foríbalẹ̀ fún ọ; gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
І зі́гнуті при́йдуть до тебе сини твоїх кри́вдників, і кла́нятись будуть до стіп твоїх ніг усі нена́висники, і тебе будуть кликати: Місто Господнє, Сіон Святого Ізраїлевого!
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá, Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé àti ayọ̀ àtìrandíran.
За те, що була ти поки́нута та осору́жна, о до́чко Сіону, і через тебе ніхто не ходив, то вчиню́ тебе славою вічною, радістю з роду в рід!
16 Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
І бу́деш ти ссати молоко із наро́дів, і гру́ди царів будеш сса́ти, і пізнаєш, що Я — то Господь, твій Спаси́тель, а твій Викупи́тель — Поту́жний Яковів!
17 Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ, dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ, àti irin dípò òkúta. Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
Замість міді впрова́джу Я золото, і замість заліза впрова́джу срібло́, і замість дерева — мідь, а за́мість камі́ння — залізо, і дозо́ром твоїм зроблю мир, твоїми ж начальниками — справедливість!
18 A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́, tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
В твоїм кра́ї не буде вже чуте наси́лля, руїна й спусто́шення в ме́жах твоїх, і назве́ш свої му́ри спасі́нням, а брами свої — похвало́ю!
19 Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́, tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́, nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé, àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
Удень сонце не буде тобі вже за світло, і не буде світити тобі місяць за ся́йво, бо бу́де тобі вічним світлом Госпо́дь, а твій Бог — за окра́су твою!
20 Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́, àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́; Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ, àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
Не за́йде вже сонце твоє, і місяць твій вже не схова́ється, бо бу́де тобі вічним світлом Госпо́дь, і дні жало́би твоєї покі́нчаться!
21 Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé. Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, láti fi ọláńlá mi hàn.
А наро́д твій — усі справедли́ві вони, землю вспадку́ють навіки, па́рость Моїх саджанці́в, чин Моїх рук на просла́влення!
22 Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan, èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá. Èmi ni Olúwa; ní àkókò rẹ̀, Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”
Цей мали́й стане тисячею, і наймолодший — наро́дом міцни́м! Я, Господь, цього ча́су оце приспішу́!

< Isaiah 60 >