< Isaiah 60 >

1 “Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
Vstani, zasij, kajti tvoja svetloba je prišla in Gospodova slava je vstala nad teboj.
2 Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́ ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
Kajti glej, tema bo prekrila zemljo in velika tema ljudstva, toda Gospod bo vstal nad teboj in njegova slava bo vidna na tebi.
3 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ, àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.
Pogani bodo prišli k tvoji svetlobi in kralji k siju tvojega vzhajanja.
4 “Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò. Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
Dvigni svoje oči naokoli in poglej. Vsi se zbirajo skupaj, prihajajo k tebi. Tvoji sinovi bodo prišli od daleč in tvoje hčere bodo negovane ob tvoji strani.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán, ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀; ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ, sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
Takrat boš videla in tekla skupaj in tvoje srce se bo balo in bo povečano, ker bo obilje morja obrnjeno k tebi, sile poganov bodo prišle k tebi.
6 Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani. Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá, wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́ tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
Pokrila te bo množica kamel, [enogrbi] velblodi iz Midjána in Efe, vsi tisti iz Sabe bodo prišli. Prinesli bodo zlato in kadilo in naznanjali bodo Gospodove hvalnice.
7 Gbogbo agbo ẹran ìlú Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ, àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́; wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi, bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.
Vsi kedárski tropi bodo zbrani skupaj k tebi, Nebajótovi ovni ti bodo služili. Na moj oltar bodo prišli s sprejetjem in jaz bom proslavil hišo svoje slave.
8 “Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru, gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
Kdo so ti, ki letijo kakor oblak in kakor golobice k svojim oknom?
9 Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí; ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn, pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn, fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.
Otoki bodo zagotovo čakali name in spredaj ladje iz Taršíša, da privedejo tvoje sinove od daleč, njihovo srebro in njihovo zlato z njimi, k imenu Gospoda, tvojega Boga in k Svetemu Izraelovemu, ker te je proslavil.
10 “Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́, ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
Sinovi tujcev bodo zgradili tvoja obzidja in njihovi kralji ti bodo služili, kajti v svojem besu sem te udaril, toda v svoji naklonjenosti sem imel usmiljenje nad teboj.
11 Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀, a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
Zato bodo tvoja velika vrata nenehno odprta; ne podnevi ne ponoči ne bodo zaprta, da ti bodo ljudje lahko prinašali sile poganov in da bodo lahko privedeni njihovi kralji.
12 Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun; pátápátá ni yóò sì dahoro.
Kajti narod in kraljestvo, ki ti ne bo služilo, bo propadlo; da, ti narodi bodo popolnoma opustošeni.
13 “Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀, láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi; àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
Slava Libanona bo prišla k tebi, cipresa, bor in pušpan skupaj, da olepšajo kraj mojega svetišča in kraj svojih stopal bom naredil veličasten.
14 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò wá foríbalẹ̀ fún ọ; gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Tudi sinovi tistih, ki so te prizadeli, bodo prišli, upogibajoč se k tebi in vsi, ki so te prezirali, se bodo priklonili pri podplatih tvojih stopal in imenovali te bodo: › Gospodovo mesto, Sion Svetega Izraelovega.‹
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá, Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé àti ayọ̀ àtìrandíran.
Kakor si bila zapuščena in osovražena, tako da noben človek ni šel skozi tebe, te bom naredil za večno odličnost, radost mnogih rodov.
16 Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
Prav tako boš sesala mleko poganov in sesala prsi kraljev in vedela boš, da sem jaz, Gospod, tvoj Odrešenik in tvoj Odkupitelj, Mogočni Jakobov.
17 Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ, dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ, àti irin dípò òkúta. Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
Za bron bom prinesel zlato in za železo bom prinesel srebro in za les bron in za kamne železo. Prav tako bom postavil [za] tvoje častnike mir in tvoje priganjače pravičnost.
18 A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́, tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
Nasilja ne bo več slišati v tvoji deželi niti pustošenja niti uničenja znotraj tvojih meja, temveč boš svoja obzidja imenovala Odrešenje in svoja velika vrata Hvala.
19 Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́, tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́, nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé, àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
Sonce ne bo več tvoja svetloba podnevi niti ti za sijaj luna ne bo dajala svetlobe, temveč ti bo Gospod večna svetloba in tvoj Bog tvoja slava.
20 Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́, àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́; Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ, àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
Tvoje sonce ne bo več zašlo niti se tvoja luna ne bo umaknila, kajti Gospod bo tvoja večna svetloba in dnevi tvojega žalovanja bodo končani.
21 Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé. Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, láti fi ọláńlá mi hàn.
Prav tako tvoje ljudstvo – vsi bodo pravični. Podedovali bodo deželo na veke, mladiko mojega sajenja, delo mojih rok, da bom lahko proslavljen.
22 Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan, èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá. Èmi ni Olúwa; ní àkókò rẹ̀, Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”
Najmanjši bo postal tisoč in malček mogočen narod. Jaz, Gospod, bom to pospešil ob svojem času.

< Isaiah 60 >