< Isaiah 6 >

1 Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
I det år kong Ussias døde, så jeg Herren sitte på en høi, høi trone, og slepet av hans kåpe opfylte templet.
2 Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
Serafer stod omkring ham. Seks vinger hadde hver; med to dekket han sitt åsyn, med to dekket han sine føtter, og med to fløi han.
3 Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
Og den ene ropte til den andre og sa: Hellig, hellig, hellig er Herren, hærskarenes Gud; all jorden er full av hans herlighet.
4 Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
Og tresklenes poster bevet ved de ropendes røst, og huset blev fylt med røk.
5 Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
Da sa jeg: Ve mig! Jeg er fortapt; for jeg er en mann med urene leber, og jeg bor midt iblandt et folk med urene leber, og mine øine har sett kongen, Herren, hærskarenes Gud.
6 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
Da fløi en av serafene bort til mig med en gloende sten i sin hånd; med en tang hadde han tatt den fra alteret.
7 Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
Og han rørte ved min munn med den og sa: Se, denne har rørt ved dine leber, din misgjerning er tatt bort, og din synd er sonet.
8 Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
Da hørte jeg Herrens røst: Hvem skal jeg sende, og hvem vil gå for oss? Da sa jeg: Se, her er jeg, send mig!
9 Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
Og han sa: Gå avsted og si til dette folk: Hør og hør, men forstå ikke, og se og se, men skjønn ikke!
10 Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
Gjør dette folks hjerte sløvt og gjør dets ører tunghørte og klin dets øine til, forat det ikke skal se med sine øine og ikke høre med sine ører, og dets hjerte ikke forstå og omvende sig, så det blir lægt!
11 Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
Da spurte jeg: Hvor lenge, Herre? Og han sa: Inntil byene er ødelagt og folketomme, og husene uten mennesker, og landet er ødelagt og blitt til en ørken.
12 Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
Og Herren skal drive menneskene langt bort, og tomheten blir stor i landet.
13 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”
Og er det ennu en tiendedel igjen i det, så skal også den bli fortæret. Men likesom det blir en stubb igjen av terebinten og eken når de felles, så skal en hellig sæd være den stubb som blir igjen av folket.

< Isaiah 6 >