< Isaiah 6 >

1 Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
I te tau i mate ai a Kingi Utia i kite ahau i te Ariki e noho ana i runga i te torona, he tiketike, he mea whakarewa ake ki runga, ki tonu ano hoki te temepara i te remu o tona.
2 Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
E tu ana nga herapima i runga ake i a ia: e ono nga parirau o tetahi, o tetahi; i hipokina e ia tona mata ki tetahi rua, ona waewae hoki ki tetahi rua, a ko tetahi rua hei rere mana.
3 Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
A i karanga ratou tetahi ki tetahi, i mea, He tapu, he tapu, he tapu, a Ihowa o nga mano; ki katoa te whenua i tona kororia.
4 Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
I oioi ano nga pou o nga tatau i te reo o tera i karanga ra, ki tonu te whare i te paowa.
5 Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
Na ko taku kianga ake, Aue te mate moku! ka ngaro hoki ahau; he tangata ngutu poke hoki ahau, e noho ana i waenganui i te iwi ngutu poke; kua kite nei hoki oku kanohi i te kingi, i a Ihowa o nga mano.
6 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
Na ko te rerenga mai o tetahi o nga herapima ki ahau, he waro mura i tona ringa, he mea tango mai e ia i te aata ki te kokopi.
7 Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
Whakapangia mai ana e ia ki toku mangai, me tana ki mai, Nana, kua pa tenei ki ou ngutu; na kua riro tou he, kua murua tou hara.
8 Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
Na ka rongo ahau i te reo o te Ariki e mea ana, Ko wai taku e unga ai, ko wai ta tatou hei haere? Ano ra ko ahau, Tenei ahau, ngarea ko ahau.
9 Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
Ano ra ko ia, Haere, mea atu ki tenei iwi, Rongo noa koutou, e kore e matau; titiro noa koutou, e kore e kite.
10 Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
Meinga te ngakau o tenei iwi kia ngako, o ratou taringa kia taimaha, whakamoea o ratou kanohi; kei kite o ratou kanohi, kei rongo o ratou taringa, kei matau o ratou ngakau, a ka tahuri, ka whakaorangia.
11 Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
Ano ra ko ahau, E te Ariki, kia pehea te roa? Na ka mea ia, Kia ururuatia ra ano nga pa, a kore noa he tangata hei noho, kia kore ra ano he tangata mo roto i nga whare, kia tino ururuatia rawatia ano hoki te whenua.
12 Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
Kia whakamataratia e Ihowa nga tangata ki tawhiti, a ka nui te whakarerenga i waenganui i te whenua.
13 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”
A, ki te mau ano he whakatekau i roto i a ia, ka kainga tuaruatia ano ia: ka rite ki te terepini, ki te oki, e mau tonu nei tona uho, i te mea kua tuaina; na hei uho mona te uri tapu.

< Isaiah 6 >