< Isaiah 6 >

1 Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
Léta, kteréhož umřel král Uziáš, viděl jsem Pána sedícího na trůnu vysokém a vyzdviženém, a podolek jeho naplňoval chrám.
2 Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
Serafínové stáli nad ním. Šest křídel měl každý z nich: dvěma zakrýval tvář svou, a dvěma přikrýval nohy své, a dvěma létal.
3 Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
A volal jeden k druhému, říkaje: Svatý, svatý, svatý Hospodin zástupů, plná jest všecka země slávy jeho.
4 Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
A pohnuly se podvoje veřejí od hlasu volajícího, a dům plný byl dymu.
5 Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
I řekl jsem: Běda mně, jižť zahynu, proto že jsem člověk poškvrněné rty maje, k tomu u prostřed lidu rty poškvrněné majícího bydlím, a že krále Hospodina zástupů viděly oči mé.
6 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
I přiletěl ke mně jeden z serafínů, maje v ruce své uhel řeřavý, kleštěmi vzatý z oltáře,
7 Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
A dotekl se úst mých, a řekl: Aj hle, dotekl se uhel tento úst tvých; nebo odešla nepravost tvá, a hřích tvůj shlazen jest.
8 Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
Potom slyšel jsem hlas Pána řkoucího: Koho pošli? A kdo nám půjde? I řekl jsem: Aj já, pošli mne.
9 Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
On pak řekl: Jdi, a rci lidu tomu: Slyšte slyšíce, a nerozumějte, a hleďte hledíce, a nepoznávejte.
10 Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
Zatvrď srdce lidu toho, a uši jeho zacpej, a oči jeho zavři, aby neviděl očima svýma, a ušima svýma neslyšel, a srdcem svým nerozuměl, a neobrátil se, a nebyl uzdraven.
11 Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
A když jsem řekl: Až dokud, Pane? i odpověděl: Dokudž nezpustnou města, tak aby nebylo žádného obyvatele, a domové, aby nebylo v nich žádného člověka, a země docela nezpustne,
12 Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
A nevzdálí Hospodin všelikého člověka, a nebude dokonalého zpuštění u prostřed země;
13 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”
Dokudž ještě v ní nebude desateré zhouby, a teprv zkažena bude. Ale jakož ono jilmoví, a jako doubí onoho náspu podporou jest, tak símě svaté jest podpora její.

< Isaiah 6 >