< Isaiah 59 >

1 Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
Ampa ara Awurade nsa nyɛ tiaa sɛ ɛrennye nkwa, na nʼasom nyɛ den sɛ ɛrente asɛm.
2 Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
Nanso mo amumɔyɛ na atetew mo ne mo Nyankopɔn ntam; mo bɔne ama nʼanim ahintaw mo, a enti ɔrente.
3 Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
Na mogya akeka mo nsa ho, afɔdi asra mo nsateaa ho. Mo ano akeka atosɛm, mo tɛkrɛma de amumɔyɛsɛm di nseku.
4 Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
Obiara nhwehwɛ atɛntrenee; obiara mfa nokwaredi mmɔ ne nkurow. Wɔde wɔn ho to nsɛnhuhuw so na wotwa nkontompo; wonyinsɛn ɔhaw na wɔwo bɔne.
5 Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
Wosow nhurutoa nkesua na wɔnwen ananse ntontan. Nea odi wɔn nkesua biara bewu, mu baako nso bɔ a, ɛpae ahurutoa.
6 Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
Wɔn ntontan nye mma adurade; wɔrentumi mfa nea wɔyɛ nkata wɔn ho. Wɔn nneyɛe yɛ nneyɛe bɔne, na wodi akakabensɛm.
7 Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
Wotu mmirika kɔyɛ bɔne; wɔnkyɛ opira ne awudi ho. Baabiara a wɔbɛkɔ no, wɔsɛe hɔ pasaa.
8 Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
Asomdwoe kwan no, wonnim; atɛntrenee nni wɔn akwan so. Wɔadan wɔn akwan kɔntɔnkye obiara a ɔnantew so no rennya asomdwoe.
9 Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
Enti atɛntrenee ne yɛn ntam aware, na adetrenee mmɛn yɛn. Yɛhwehwɛ hann, nanso ne nyinaa yɛ sum; nea ɛhyerɛn, nanso yɛnam sum kabii mu.
10 Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
Te sɛ anifuraefo no, yɛkeka wɔ afasu ho hwehwɛ ɔkwan te sɛ nnipa a wonni ani. Owigyinae no yehintihintiw sɛnea onwini adwo; yedu ahoɔdenfo mu a yɛte sɛ awufo.
11 Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
Yɛn nyinaa woro so te sɛ sisi; yɛde awerɛhow kurum sɛ mmorɔnoma. Yɛhwehwɛ atɛntrenee nso yenhu bi; ogye, nanso ɛwɔ akyirikyiri.
12 Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
Efisɛ, yɛn mfomso adɔɔso wɔ wʼani so, na yɛn bɔne di adanse tia yɛn. Yɛn mfomso da yɛn anim daa, na yegye yɛn amumɔyɛ to mu:
13 ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
atuatew ne nkontompo a etia Awurade, yɛn akyi a yɛdan kyerɛ yɛn Nyankopɔn, nhyɛso ne atuatew a yɛfoa so, atosɛm a efi koma mu a yɛka.
14 Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
Enti wɔapam atɛntrenee kɔ nʼakyi, na adetrenee akogyina baabi; nokware ahwe ase wɔ mmɔnten so nokwaredi ntumi mma mu.
15 A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
Nokware nni baabiara, obiara a ɔtwe ne ho fi bɔne ho no bɛyɛ ɔtamfo. Awurade hwɛe na ansɔ nʼani sɛ atɛntrenee nni hɔ.
16 Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
Ohuu sɛ obiara nni hɔ, ɛyɛɛ no nwonwa sɛ obiara nni hɔ a ɔbɛpata; enti ɔno ankasa basa dii nkwagye ho dwuma maa no, na ne trenee wowaw no.
17 Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
Ɔhyɛɛ trenee sɛ nkatabo, ne nkwagye dadekyɛw wɔ ne ti so. Ɔhyɛɛ aweretɔ ntade na ofuraa mmɔdemmɔ sɛ ntama.
18 Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
Obegyina nea wɔayɛ so atua so ka nʼatamfo benya nʼabufuwhyew wɔn a wɔne no ayɛ dɔm benya so akatua; nsupɔw no nso obetua wɔn ka sɛnea ɛfata wɔn.
19 Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
Efi atɔe fam, nnipa besuro Awurade din na efi apuei, wɔde nidi bɛma nʼanuonyam. Na ɔbɛba sɛ asu a ayiri tɛnn na Awurade ahomegu repia no.
20 “Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
“Ogyefo no bɛba Sion, na obeyi amumɔyɛsɛm nyinaa afi Yakob asefo mu,” sɛɛ na Awurade se.
21 “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.
“Me de, eyi yɛ me ne wɔn apam,” sɛnea Awurade se ni. “Me Honhom a ɔwɔ mo so, ne me nsɛm a mede ahyɛ mo anom, remfi mo anom, anaa mo mma, ne mo mma asefo anom, efi saa bere yi kosi daa apem,” sɛɛ na Awurade se.

< Isaiah 59 >