< Isaiah 59 >

1 Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
Iată, mâna DOMNULUI nu s-a scurtat, încât să nu poată salva, nici urechea lui nu s-a îngreunat, încât să nu poată auzi;
2 Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
Ci nelegiuirile voastre au făcut o despărţire între voi şi Dumnezeul vostru şi păcatele voastre au ascuns faţa lui de voi, ca să nu asculte.
3 Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
Fiindcă mâinile vă sunt întinate cu sânge şi degetele voastre cu nelegiuire; buzele voastre au vorbit minciuni, limba voastră a bolborosit perversitate.
4 Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
Nimeni nu strigă după dreptate, nimeni nu pledează pentru adevăr, ei se încred în deşertăciune şi vorbesc minciuni; concep ticăloşie şi nasc nelegiuire.
5 Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
Clocesc ouă de năpârcă şi ţes pânză de păianjen, cel ce mănâncă ouăle lor moare şi dacă se striveşte unul, iese o viperă.
6 Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
Pânzele lor nu vor deveni veşminte, nici nu se vor acoperi cu faptele lor, faptele lor sunt fapte ale nelegiuirii şi actul de violenţă este în mâinile lor.
7 Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
Picioarele lor aleargă la rău şi se grăbesc să verse sânge nevinovat, gândurile lor sunt gânduri ale nelegiuirii; risipire şi nimicire sunt pe cărările lor.
8 Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
Calea păcii ei nu o cunosc; şi nu este judecată în umbletele lor, şi-au făcut cărări strâmbe, oricine umblă în ele nu va cunoaşte pace.
9 Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
De aceea judecata este departe de noi, şi dreptatea nu ne ajunge, aşteptăm lumină, dar iată, întuneric; strălucire, dar umblăm în întunecime.
10 Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
Bâjbâim căutând zidul ca orbii şi bâjbâim ca şi cum nu am avea ochi, ne poticnim la amiază ca noaptea; suntem în locuri pustiite ca morţi.
11 Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
Răcnim toţi ca urşii şi jelim mult ca porumbeii, căutăm judecata, dar nu este niciuna; salvarea, dar este departe de noi.
12 Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
Fiindcă fărădelegile noastre s-au înmulţit înaintea ta şi păcatele noastre mărturisesc împotriva noastră, căci fărădelegile noastre sunt cu noi; şi cât despre nelegiuirile noastre, le cunoaştem;
13 ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
Făcând fărădelege şi minţind împotriva DOMNULUI şi îndepărtându-ne de Dumnezeul nostru, vorbind asuprire şi răzvrătire, concepând şi rostind din inimă cuvintele minciunii.
14 Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
Şi judecata s-a întors înapoi şi dreptatea stă departe, căci adevărul a căzut în stradă şi echitatea nu poate intra.
15 A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
Da, adevărul lipseşte; şi cel ce se depărtează de rău se face pe sine o pradă, şi DOMNUL a văzut aceasta şi nu i-a plăcut că nu este judecată.
16 Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
Şi a văzut că nu este om şi s-a minunat că nu este mijlocitor, de aceea braţul său i-a adus salvare; şi dreptatea lui, ea l-a sprijinit.
17 Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
Căci a îmbrăcat dreptatea ca pe un pieptar şi şi-a pus pe cap un coif al salvării; şi a îmbrăcat veşmintele răzbunării ca îmbrăcăminte şi a fost acoperit cu zel precum cu o mantie.
18 Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
Conform faptelor lor, astfel va răsplăti el, furie potrivnicilor săi, recompensă duşmanilor săi; insulelor le va răsplăti fapta lor.
19 Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
Astfel cei de la apus se vor teme de numele DOMNULUI, şi de gloria lui cei de la răsăritul soarelui. Când duşmanul va intra ca un potop, Duhul DOMNULUI va ridica un steag împotriva lui.
20 “Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
Şi Răscumpărătorul va veni în Sion şi la cei din Iacob care se vor întoarce de la fărădelege, spune DOMNUL.
21 “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.
Cât despre mine, acesta este legământul meu cu ei, spune DOMNUL: Duhul meu care este peste tine şi cuvintele mele pe care le-am pus în gura ta, nu se vor depărta de gura ta, nici din gura seminţei tale, nici din gura seminţei seminţei tale, spune DOMNUL, de acum şi pentru totdeauna.

< Isaiah 59 >