< Isaiah 59 >

1 Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
Oto ręka PANA nie jest skrócona, aby nie mogła zbawić, ani jego ucho nie jest przytępione, aby nie mogło wysłuchać.
2 Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
Ale wasze nieprawości uczyniły przepaść między wami a waszym Bogiem i wasze grzechy sprawiły, że ukrył twarz przed wami, tak że nie słyszy.
3 Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
Wasze ręce bowiem są splamione krwią, a wasze palce – nieprawością. Wasze wargi mówią kłamstwa, a wasz język szepce przewrotności.
4 Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
Nikt nie woła o sprawiedliwość i nikt się nie spiera o prawdę. Ufają marności i mówią kłamstwa, wyrządzają krzywdę i rodzą nieprawość.
5 Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
Wylęgają jaja węża i tkają pajęczynę. Kto spożywa ich jaja, umiera, a jeśli je stłucze, wykluwa się żmija.
6 Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
Ich pajęczyny nie nadają się na szatę ani nie okryją się swoimi uczynkami. Ich uczynki to uczynki nieprawości i w ich rękach są czyny przemocy.
7 Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
Ich nogi biegną do zła i spieszą się do przelewania niewinnej krwi. Ich myśli są myślami nieprawości, spustoszenie i zniszczenie na ich drogach.
8 Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
Drogi pokoju nie znają i nie ma na ich drogach sprawiedliwości. Uczynili sobie kręte ścieżki; ten, kto po nich chodzi, nie zazna pokoju.
9 Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
Dlatego sąd jest daleki od nas i nie dociera do nas sprawiedliwość. Czekamy na światłość – a oto ciemność, na jasność – ale kroczymy w mrokach.
10 Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
Macamy ściany jak ślepi, macamy, jakbyśmy oczu nie mieli. Potykamy się w południe jak o zmierzchu; w miejscach opustoszałych – jak umarli.
11 Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
Ryczymy wszyscy jak niedźwiedzie, jak gołębie ciągle wzdychamy; oczekujemy sądu, ale go nie ma; [oczekujemy] na wybawienie, ale jest od nas daleko.
12 Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
Rozmnożyły się bowiem nasze przestępstwa przed tobą i nasze grzechy świadczą przeciwko nam, ponieważ nasze nieprawości są przy nas i uznajemy swoje przestępstwa;
13 ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
Zgrzeszyliśmy i kłamaliśmy przeciw PANU i odwróciliśmy się od naszego Boga, aby nie chodzić za nim; mówiliśmy o ucisku i buncie, obmyślaliśmy i wypowiadaliśmy słowa kłamliwe ze swego serca.
14 Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
Dlatego sąd został wycofany i sprawiedliwość stoi z daleka, bo prawda runęła na ulicy, a prawość nie może tam wejść.
15 A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
Tak, prawda zginęła, a ten, kto odstępuje od zła, pada ofiarą łupu. PAN to widział i nie podobało mu się, że nie ma sądu.
16 Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
Widział, że nie ma żadnego człowieka i zdziwił się, że nie ma nikogo, kto by się wstawił. Dlatego jego ramię przyniosło mu zbawienie i jego własna sprawiedliwość była jego podporą.
17 Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
Przyodział się bowiem w sprawiedliwość jak w pancerz i włożył hełm zbawienia na swą głowę. Przyoblekł się w odzienie pomsty jak w szatę i okrył się gorliwością jak płaszczem.
18 Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
Według uczynków, stosownie do nich, odpłaci gniewem swoim przeciwnikom, odwetem swoim wrogom; wyspom odpłaci odwetem.
19 Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
I ci, którzy są na zachodzie, będą się bali imienia PANA, i ci, którzy na wschodzie – jego chwały. Gdy wróg przyjdzie jak rzeka, Duch PANA przepędzi go.
20 “Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
Przyjdzie bowiem Odkupiciel do Syjonu i do tych spośród Jakuba, którzy odwracają się od występków, mówi PAN.
21 “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.
A to będzie moje przymierze z nimi, mówi PAN: Mój Duch, który jest w tobie, i moje słowa, które włożyłem w twoje usta, nie odstąpią od twoich ust ani od ust twego potomstwa, ani od ust potomków twego potomstwa, mówi PAN, odtąd aż na wieki.

< Isaiah 59 >