< Isaiah 59 >

1 Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
Atĩrĩrĩ, ti-itherũ guoko kwa Jehova ti kuonju atĩ gũtingĩhota kũhonokania, o na kana gũtũ gwake gũkagĩa njiika atĩ gũtingĩhota kũigua.
2 Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
No rĩrĩ, mawaganu manyu nĩmo mamũtigithanĩtie na Ngai wanyu; namo mehia manyu nĩmo matũmĩte amũhithe ũthiũ wake, akarega kũmũigua.
3 Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
Nĩgũkorwo moko manyu nĩmathaahĩte nĩ ũiti wa thakame, nacio ciara cianyu ikaiyũra wĩhia. Tũnua twanyu nĩtwarĩtie ndeto cia maheeni, na nĩmĩ cianyu ikangʼungʼuaga o ndeto cia waganu.
4 Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
Gũtirĩ mũndũ wendaga ciira wa kĩhooto, o na kana ageciirĩrĩra na njĩra ya ma. Mehokaga ngarari cia tũhũ na makaaria ndeto cia maheeni; magĩaga nda cia mathĩĩna na magaciara waganu.
5 Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
Mahaana ta makomeire matumbĩ ma nduĩra, na makaamba mĩtego ya rũrenda rwa mbũmbũĩ. Mũndũ o wothe ũrĩa ũngĩrĩa matumbĩ macio no gũkua akuaga, na o itumbĩ rĩahehenjwo rĩtũrĩkaga nduĩra.
6 Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
Rũrenda rũu rwao nĩ rwa tũhũ rũtingĩtumwo nguo; matiingĩhumbĩra na kĩrĩa mathondekaga naruo. Mawĩra mao nĩ mawĩra ma waganu, na moko mao maiyũrĩte ciĩko cia haaro.
7 Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
Magũrũ mao mahanyũkaga makehie; mahiũhaga magaite thakame ya mũndũ ũtehĩtie. Meciiria mao no meciiria ma ũũru; na kũrĩa guothe mathiiaga matigaga gũkirĩte ihooru na mwanangĩko.
8 Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
Njĩra ya thayũ matimĩũĩ; na mĩthiĩre yao ti ya gũtuanĩra ciira na kĩhooto. Metemeire njĩra njogomu; gũtirĩ mũndũ ũcigeragĩra akagĩa na thayũ.
9 Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
Nĩ ũndũ ũcio ciira wa kĩhooto ũrĩ kũraya na ithuĩ, naguo ũthingu ndũtũkinyagĩra. Tũcaragia ũtheri, no tuonaga o nduma; tũgacaria ũkengu, no tũkagerera kũrĩa kũrĩ na mairia matumanu.
10 Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
Tũhambataga rũthingo ta mũtumumu, na tũgeetherera njĩra ta andũ matarĩ maitho. Tũhĩngagwo mũthenya barigici o ta rĩrĩa kũrĩ mairia; tũrĩ gatagatĩ ka andũ arĩa marĩ hinya, tũhaanaga ta andũ akuũ.
11 Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
Ithuothe tũraramaga o ta nduba; tũcakayaga na kĩeha ta ndutura. Tũcaragia ũhoro wa gũtuĩrwo ciira na kĩhooto, na tũtingĩwona o na atĩa; tũgacaria ũhoro wa ũhonokanio, no ũgatũraihĩrĩria mũno.
12 Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
Nĩgũkorwo mahĩtia maitũ nĩ maingĩ maitho-inĩ maku, namo mehia maitũ makoimbũra ũrĩa tũtariĩ. Hĩndĩ ciothe mahĩtia maitũ makoragwo hamwe na ithuĩ, namo mehia maitũ nĩtũmooĩ mothe:
13 ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
namo nĩ ũremi na gũkaana Jehova, na kũhutatĩra Ngai witũ, na kwaragia ndeto cia kũhinyanĩrĩria, na kũregana na watho, na kwaria ndeto cia maheeni iria ngoro ciitũ ithugundĩte.
14 Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
Nĩ ũndũ ũcio nĩtwagĩte ciira wa kĩhooto, naguo ũthingu ũgatũraihĩrĩria; naguo ũhoro wa ma ũkagũa njĩra-inĩ, naguo ũrũngĩrĩru ũkaagĩrwo mweke.
15 A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
Ũhoro wa ma ndũrĩ handũ ũngĩoneka, nake mũndũ ũrĩa wĩthemaga ũũru agatuĩka mũndũ wa kũguĩmwo. Nake Jehova akĩona ũndũ ũcio, ũkĩaga kũmũkenia, tondũ gũtiatuanagĩrwo ciira na kĩhooto.
16 Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
Ningĩ akĩona atĩ gũtiarĩ mũndũ o na ũmwe wagĩrĩire, na akĩgega tondũ gũtiarĩ na mũteithũrani; nĩ ũndũ ũcio guoko gwake mwene nĩkuo kwamũhonokirie, naguo ũthingu wake mwene ũkĩmũtiirĩrĩra.
17 Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
Agĩcooka akĩĩhumba ũthingu taarĩ gako gake ga kũmũgitĩra gĩthũri, na agĩĩkĩra ngũbia ya kĩgera ya ũhonokio mũtwe; naguo ũhoro wa kũrĩhanĩria akĩwĩĩhumba taarĩ nguo, na akĩĩhotora kĩyo taarĩ nguo ndaaya.
18 Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
O ta ũrĩa ciĩko ciao itariĩ, ũguo noguo akaarĩhana, arĩhe thũ ciake na mangʼũrĩ, nao andũ arĩa marĩ muku nake amacookererie ũũru wao; andũ arĩa matũũraga icigĩrĩra-inĩ-rĩ, erĩhĩrie na kũmagera ngero o ũrĩa kwagĩrĩire.
19 Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, andũ nĩmagetigĩra rĩĩtwa rĩa Jehova kuuma ithũĩro, na nĩmagatĩĩa riiri wake kuuma irathĩro rĩa riũa. Nĩgũkorwo agooka ta rũũĩ ruunĩte, rũgatherera na ihenya, rũtindĩkĩtwo nĩ mĩhũmũ ya Jehova.
20 “Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
“Mũkũũri nĩagooka Zayuni, na akinye kũrĩ andũ a Jakubu arĩa maherete mehia mao,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
21 “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.
Ningĩ Jehova ekuuga atĩrĩ, “Ha ũhoro wakwa-rĩ, gĩkĩ nĩkĩo kĩrĩkanĩro kĩrĩa ndarĩkanĩire nao, atĩ Roho wakwa, ũrĩa ũrĩ igũrũ rĩaku, na ciugo ciakwa iria njĩkĩrĩte kanua gaku, itirĩ hĩndĩ ikehera kuuma kanua gaku, kana ciehere kuuma tũnua twa ciana ciaku, o na kana ciehere kuuma tũnua twa njiaro ciao, kuuma rĩu nginya tene na tene,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.

< Isaiah 59 >