< Isaiah 59 >
1 Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
Aj, neníť ukrácena ruka Hospodinova, aby nemohla zachovati, aniž jest obtíženo ucho jeho, aby nemohlo slyšeti.
2 Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
Ale nepravosti vaše rozloučily vás s Bohem vaším, a hříchové vaši to způsobili, že skryl tvář před vámi, aby neslyšel.
3 Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
Nebo ruce vaše jsou poškvrněné krví, a prstové vaši nepravostí; rtové vaši mluví lež, jazyk váš vynáší převrácenost.
4 Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
Není žádného, ješto by se zasadil o spravedlnost, aniž jest kdo, ješto by zastával pravdy. Doufají v marnost, a mluví daremné věci; počínají nátisk, a rodí nepravost.
5 Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
Vejce bazališková vyseděli, a plátna pavoukového natkali. Kdož by jedl vejce jejich, umře; pakli je roztlačí, vynikne ještěrka.
6 Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
Plátna jejich nehodí se na roucho, aniž se odějí dílem svým; skutkové jejich skutkové nepravosti, a dílo ukrutnosti jest v rukou jejich.
7 Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
Nohy jejich k zlému běží, a pospíchají k vylévání krve nevinné. Myšlení jejich jsou myšlení nepravá, zpuštění a setření jest na cestách jejich.
8 Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
Cesty pokoje neznají, a není žádné spravedlnosti v šlepějích jejich. Stezky své převracejí tajně; kdožkoli po nich chodí, nemívá pokoje.
9 Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
Protož vzdálil se od nás soud, a nedochází nás spravedlnost. Čekáme-li na světlo, aj, tma, pakli na blesk, v mrákotách chodíme.
10 Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
Makáme jako slepí stěnu, a jako bychom žádných očí neměli, šámáme. Urážíme se o poledni jako v soumrak, u veliké hojnosti podobni jsme mrtvým.
11 Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
Mumleme všickni my jako nedvědi, a jako holubice ustavičně lkáme. Očekáváme na soud, ale není ho, na vysvobození, ale daleké jest od nás.
12 Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
Nebo rozmnožena jsou přestoupení naše před tebou, a hříchové naši svědčí proti nám, poněvadž přestoupení naše jsou při nás, i nepravosti naše. Známeť to,
13 ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
Že jsme se zpronevěřili, a lhali Hospodinu, a odvrátili se od následování Boha svého, že jsme mluvili o nátisku a odvrácení, že jsme ukládali a vynášeli z srdce slova lživá,
14 Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
Tak že odvrácen jest nazpět soud, a spravedlnost zdaleka stojí; nebo klesla na ulici pravda, a pravost nemá průchodu.
15 A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
Nýbrž zhynula pravda, a ten, kdož se uchyluje od zlého, loupeži bývá vydán; což vidí Hospodin, a nelíbí se to jemu, že není žádného soudu.
16 Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
Když tedy viděl, že není žádného muže, až se užasl, že není žádného prostředníka. A protož vysvobození jemu způsobilo rámě jeho, a spravedlnost jeho sama jej zpodepřela.
17 Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
Nebo oblékl spravedlnost jako pancíř, a lebka spasení na hlavě jeho. Oblékl se v roucho pomsty jako v sukni, a oděl se horlivostí jako pláštěm,
18 Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
Aby podlé skutků, aby podlé nich odplacel prchlivostí protivníkům svým, odměnu nepřátelům svým, i ostrovům odplatu aby dával.
19 Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
I budou se báti na západ jména Hospodinova, a na východu slunce slávy jeho, když se přivalí jako řeka nepřítel, jejž duch Hospodinův preč zažene.
20 “Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
Neboť přijde k Sionu vykupitel, a k těm, kteříž se odvracují od přestoupení v Jákobovi, praví Hospodin.
21 “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.
Tatoť pak bude smlouva má s nimi, praví Hospodin: Duch můj, kterýž jest v tobě, a slova má, kteráž jsem vložil v ústa tvá, neodejdouť od úst tvých, ani od úst semene tvého, ani od úst potomků semene tvého, praví Hospodin, od tohoto času až na věky.