< Isaiah 58 >

1 “Kígbe rẹ̀ sókè, má ṣe fàsẹ́yìn. Gbé ohùn rẹ sókè bí i ti fèrè. Jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún àwọn ènìyàn mi, ọ̀tẹ̀ wọn, àti fún ilé Jakọbu ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
“Monteɛ mu dennen, monnnyae. Momma mo nne so sɛ torobɛnto. Mompae mu nka me nkurɔfo atuatew nkyerɛ wɔn na monka Yakobfi nso nnebɔne nkyerɛ no.
2 Nítorí ọjọ́ dé ọjọ́ ni wọ́n ń wá mi kiri; wọ́n ṣe bí ẹni ní ìtara láti mọ ọ̀nà mi, àfi bí ẹni pé wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè kan tí ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà tí òun kò sì tí ì kọ àṣẹ Ọlọ́run rẹ̀. Wọ́n ń béèrè lọ́wọ́ mi fún ìpinnu nìkan wọ́n sì ṣe bí ẹni ń tara fún Ọlọ́run láti súnmọ́ ọ̀dọ̀ wọn.
Da biara da wɔhwehwɛ me; ayɛ sɛ wɔpere sɛ wobehu mʼakwan, te sɛ wɔyɛ ɔman a wɔyɛ nea ɛteɛ na wɔmpoo ne Nyankopɔn ahyɛde. Wobisa me hɔ gyinae a ɛteɛ na ayɛ sɛ wɔpɛ sɛ Onyankopɔn bɛn wɔn.
3 Wọ́n wí pé, ‘Èéṣe tí àwa fi ń gbààwẹ̀, tí ìwọ kò sì tí ì rí? Èéṣe tí àwa fi rẹra wa sílẹ̀, tí ìwọ kò sì tí ì ṣe àkíyèsí?’ “Síbẹ̀síbẹ̀ ní ọjọ́ àwẹ̀ yín, ẹ̀yin ń ṣe bí ó ti wù yín ẹ sì ń pọ́n àwọn òṣìṣẹ́ yín gbogbo lójú.
Wɔka se, ‘Adɛn nti na yɛadi mmuada na woanhu yi? Adɛn nti na yɛabrɛ yɛn ho ase, na woanhwɛ yi?’ “Nanso mo mmuada da no, moyɛ nea mopɛ na musisi mo adwumayɛfo nyinaa.
4 Àwẹ̀ yín sì parí nínú ìjà àti asọ̀, àti lílu ọmọnìkejì ẹni pa pẹ̀lú ìkùùkuu. Ẹ̀yin kò le è gbààwẹ̀ bí ẹ ti ń ṣe lónìí kí ẹ sì retí kí a gbọ́ ohùn un yín ní ibi gíga.
Ntɔkwaw ne akasakasa na mode wie mo mmuadadi, ne akuturuku a mode bobɔ mo ho. Morentumi nni mmuada sɛnea moyɛ no nnɛ yi na moahwɛ anim sɛ wɔbɛte mo nne wɔ ɔsoro.
5 Ǹjẹ́ èyí ha ni irú àwẹ̀ tí mo yàn bí, ọjọ́ kan ṣoṣo fún ènìyàn láti rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀? Ó ha jẹ pe kí ènìyàn tẹ orí rẹ̀ ba bí i koríko lásán ni bí àti sísùn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú? Ṣé ohun tí ẹ̀ ń pè ní àwẹ̀ nìyí, ọjọ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa?
Eyi ne mmuadadi a mepɛ ana? Da koro pɛ a onipa de brɛ ne ho ase no ana? Ɛne sɛ obi si ne ti ase te sɛ mfea na ɔtena atweaatam so ne nsõ mu nko ara ana? Eyi na mofrɛ no mmuadadi, da a ɛsɔ Awurade ani yi ni ana?
6 “Ǹjẹ́ irú àwẹ̀ tí mo ti yàn kọ́ ni èyí: láti já gbogbo ẹ̀wọ̀n àìṣòdodo àti láti tú gbogbo okùn àjàgà, láti tú gbogbo àwọn ti à ń ni lára sílẹ̀ àti láti fọ́ gbogbo àjàgà?
“Saa mmuadadi yi na mepɛ: sɛ mubeyiyi ntɛnkyew nkɔnsɔnkɔnsɔn na moasan konnua ahama, sɛ mubegyaa wɔn a wɔhyɛ wɔn so na moabubu konnua biara.
7 Kì í ha á ṣe láti pín oúnjẹ yín fún àwọn tí ebi ń pa àti láti pèsè ibùgbé fún àwọn òtòṣì tí ń rìn káàkiri. Nígbà tí ẹ bá rí ẹni tí ó wà níhòhò, láti daṣọ bò ó, àti láti má ṣe lé àwọn ìbátan yín sẹ́yìn?
So ɛnsɛ sɛ mo ne wɔn a ɔkɔm de wɔn kyɛ mo aduan na moma ohiani a ɔnenam no baabi tena; na muhu nea ɔda adagyaw a mumfura no ntama na munnyi mo ani mfi mo ankasa mo nkurɔfo ne mo abusuafo so ana?
8 Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ rẹ yóò tàn jáde bí òwúrọ̀ àti ìmúláradá rẹ yóò farahàn kíákíá; nígbà náà ni òdodo rẹ yóò sì lọ níwájú rẹ, ògo Olúwa yóò sì jẹ́ ààbò lẹ́yìn rẹ.
Ɛno na mo hann bepue te sɛ ahemadakye, na mo ayaresa aba ntɛm so; afei mo trenee bedi mo anim, na Awurade anuonyam bɛbɔ mo kyidɔm.
9 Nígbà yìí ni ẹ̀yin yóò pè, tí Olúwa yóò sì dáhùn; ẹ̀yin yóò kígbe fún ìrànlọ́wọ́, òun yóò sì wí pé, Èmi nìyí. “Bí ìwọ bá mú àjàgà aninilára, nínà ìka àlébù àti sísọ ọ̀rọ̀ asán kúrò láàrín rẹ,
Afei mobɛfrɛ, na Awurade begye mo so; mobɛteɛ mu ahwehwɛ mmoa, na ɔbɛka se: Mini. “Sɛ muyi nhyɛso konnua, nsa a moteɛ wɔ nnipa so ne ntwatoso fi hɔ,
10 àti bí ẹ̀yin bá ná ara yín bí owó nítorí àwọn tí ebi ń pa tí ẹ sì tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí à ń ni lára lọ́rùn, nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóò ràn nínú òkùnkùn, àti òru yín yóò dàbí ọ̀sán gangan.
na sɛ mohaw mo ho ma wɔn a ɔkɔm de wɔn na moma wɔn a wɔhyɛ wɔn so no nea ehia wɔn a, ɛno de, mo akanea bɛhyerɛn wɔ sum mu, na mo anadwo bɛyɛ sɛ owigyinae.
11 Olúwa yóò máa tọ́ ọ yín nígbà gbogbo; òun yóò tẹ́ gbogbo àìní yín lọ́rùn ní ilẹ̀ tí oòrùn ń tan ìmọ́lẹ̀ yóò sì fún egungun rẹ lókun. Ìwọ yóò sì dàbí ọgbà tí a bomirin dáradára, àti bí orísun tí omi rẹ̀ kì í gbẹ.
Awurade bɛkyerɛ mo kwan bere biara; ɔbɛma mo nea ehia mo wɔ asase wosee so na ɔbɛhyɛ mo nipadua den. Mobɛyɛ sɛ turo a wogugu so nsu yiye, sɛ asuwa a mu nsu nyow da.
12 Àwọn ènìyàn rẹ yóò tún ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì gbé ìpìlẹ̀ àtijọ́-tijọ́ ró a ó sì pè ọ́ ní alátúnṣe ògiri tí ó ti wó àti olùmúbọ̀sípò àwọn òpópónà tí ènìyàn gbé inú rẹ̀.
Mo nkurɔfo bɛsan asi teteete nnwiriwii no, na wɔato fapem a akyɛ no; wɔbɛfrɛ mo Nea Osiesie Afasu a Abubu no, Nea Ogye Atenae Si Hɔ.
13 “Bí ìwọ bá pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́, àti ṣíṣe bí ó ti wù ọ́ ni ọjọ́ mímọ́ mi, bí ìwọ bá pe ọjọ́ ìsinmi ní ohun dídùn àti ọjọ́ mímọ́ Olúwa ní ohun ọ̀wọ̀ àti bí ìwọ bá bu ọlá fún un láti máa bá ọ̀nà tìrẹ lọ àti láti má ṣe bí ó ti wù ọ́ tàbí kí o máa sọ̀rọ̀ aláìníláárí,
“Sɛ mohwɛ mo anammɔntu so yiye Homeda na moanyɛ nea mopɛ wɔ me da kronkron no, sɛ mofrɛ Homeda no anigye da na mudi Awurade da kronkron no ni na moamfa mo ara mo akwan so na moanyɛ nea mopɛ anaa moanka nsɛnhunu a,
14 nígbà náà ni ìwọ yóò ní ayọ̀ nínú Olúwa rẹ, èmi yóò sì jẹ́ kí ìwọ kí ó máa gun ibi gíga ilẹ̀ ayé, àti láti máa jàdídùn ìní ti Jakọbu baba rẹ.” Ẹnu Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.
ɛno de mubenya anigye wɔ Awurade mu na mɛma mo anantew asase no sorɔnsorɔmmea so na moato pon wɔ mo agya Yakob agyapade so.” Awurade na waka.

< Isaiah 58 >