< Isaiah 56 >
1 Èyí ni ohun ti Olúwa sọ: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.
Tako govori Gospod: »Varujte sodbo in ravnajte pravično, kajti moja rešitev duš je blizu, da pride in moja pravičnost, da se razodene.
2 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”
Blagoslovljen je človek, ki to počne in človeški sin, ki se tega oprime, ki varuje šabat pred omadeževanjem in zadržuje svojo roko pred početjem kakršnega koli zla.
3 Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀ mọ́ Olúwa sọ wí pé, “Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.” Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé, “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”
Niti ne pusti sinu tujca, ki se je pridružil Gospodu, govoriti, rekoč: › Gospod me je popolnoma ločil od svojega ljudstva.‹ Niti naj evnuh ne reče: ›Glej, jaz sem suho drevo.‹
4 Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí: “Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin
Kajti tako govori Gospod evnuhom, ki se držijo mojih šabat in izbirajo stvari, ki mi ugajajo in se držijo moje zaveze;
5 fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀ ìrántí kan àti orúkọ kan tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin, Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé tí a kì yóò ké kúrò.
celo njim bom dal, v svoji hiši in znotraj svojih zidov, prostor in ime, boljše kakor od sinov in hčera. Dal jim bom večno ime, ki ne bo iztrebljeno.
6 Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa láti sìn ín, láti fẹ́ orúkọ Olúwa àti láti foríbalẹ̀ fún un gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́ àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—
Tudi sinove tujca, ki se pridružijo Gospodu, da bi mu služili in da bi ljubili Gospodovo ime, da bi bili njegovi služabniki, vsak, kdor ohranja šabat pred tem, da bi ga omadeževal in se drži moje zaveze,
7 àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi, èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi. Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn, ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi; nítorí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”
celó pripeljal jih bom na svojo sveto goro in jih razveselil v svoji hiši molitve. Njihove žgalne daritve in njihove klavne daritve bodo sprejete na mojem oltarju, kajti moja hiša se bo imenovala hiša molitve za vsa ljudstva.‹«
8 Olúwa Olódùmarè sọ wí pé— ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ: “Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”
Gospod Bog, ki zbira Izraelove pregnance, govori: »Še bom zbral k njemu druge, poleg tistih, ki so zbrani k njemu.
9 Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá, ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!
Vse ve poljske živali, pridite, da požrete, da, vse ve živali v gozdu.
10 Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú, gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀; gbogbo wọn jẹ́ adití ajá, wọn kò lè gbó; wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá, wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.
Njegovi stražarji so slepi. Vsi so nevedni, vsi so nemi psi, ne morejo lajati; spijo, legajo, radi dremajo.
11 Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀; wọn kì í ní ànító. Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye; olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.
Da, pohlepni psi so, ki nikoli ne morejo imeti dovolj in pastirji, ki ne morejo razumeti. Vsi gledajo na svojo lastno pot, vsak za svojim dobičkom, od svoje meje.
12 Igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn ni wí pé, “Wá, fún mi ní ọtí wáìnì! Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó ọ̀la yóò sì dàbí òní, tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Pridite, pravijo: ›Šel bom po vino in nalili se bomo z močno pijačo in jutrišnji dan bo kakor ta dan in mnogo obilnejši.‹«