< Isaiah 56 >

1 Èyí ni ohun ti Olúwa sọ: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.
Astfel spune DOMNUL: Păziţi judecata şi faceţi dreptate, fiindcă salvarea mea este aproape să vină şi dreptatea mea să fie revelată.
2 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”
Binecuvântat este omul care face aceasta şi fiul omului care se ţine de aceasta; care ţine sabatul ca să nu îl spurce şi îşi ţine mâna de la a face vreun rău.
3 Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀ mọ́ Olúwa sọ wí pé, “Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.” Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé, “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”
Nu lăsa pe fiul străinului, care s-a alăturat DOMNULUI, să vorbească, spunând: DOMNUL m-a separat în întregime de poporul lui; nici nu lăsa pe famen să spună: Iată, eu sunt un pom uscat.
4 Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí: “Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin
Fiindcă astfel spune DOMNUL, famenilor ce ţin sabatele mele şi aleg lucrurile care îmi plac mie şi apucă legământul meu;
5 fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀ ìrántí kan àti orúkọ kan tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin, Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé tí a kì yóò ké kúrò.
Lor le voi da în casa mea şi în înăuntrul zidurilor mele un loc şi un nume mai bun decât al fiilor şi al fiicelor, le voi da un nume veşnic, ce nu va fi stârpit.
6 Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa láti sìn ín, láti fẹ́ orúkọ Olúwa àti láti foríbalẹ̀ fún un gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́ àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—
De asemenea fiii străinului, care se alătură DOMNULUI, pentru a-l servi şi pentru a iubi numele DOMNULUI, pentru a fi servitorii lui, oricine ţine sabatul ca să nu îl spurce şi apucă legământul meu;
7 àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi, èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi. Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn, ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi; nítorí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”
Chiar pe ei îi voi aduce la muntele meu sfânt şi îi voi bucura în casa mea de rugăciune, ofrandele lor arse şi sacrificiile lor vor fi primite pe altarul meu; căci casa mea se va numi casă de rugăciune pentru toate popoarele.
8 Olúwa Olódùmarè sọ wí pé— ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ: “Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”
Domnul DUMNEZEU care adună pe proscrişii lui Israel spune: Voi aduna încă şi pe alţii la el, pe lângă cei adunaţi la el.
9 Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá, ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!
Voi, toate fiarele câmpului, veniţi să mâncaţi, da, voi, toate fiarele din pădure.
10 Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú, gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀; gbogbo wọn jẹ́ adití ajá, wọn kò lè gbó; wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá, wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.
Paznicii lui sunt orbi, sunt toţi neştiutori, ei sunt toţi câini muţi, nu pot lătra, dormind, stând întinşi, iubind să dormiteze.
11 Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀; wọn kì í ní ànító. Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye; olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.
Da, sunt câini lacomi care nu pot avea niciodată destul şi sunt păstori care nu pot înţelege, toţi privesc la propria cale, fiecare la câştigul său, din partea sa.
12 Igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn ni wí pé, “Wá, fún mi ní ọtí wáìnì! Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó ọ̀la yóò sì dàbí òní, tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Veniţi, spun ei, voi aduce vin şi ne vom umple cu băutură tare; şi mâine va fi ca astăzi [şi] mult mai abundent.

< Isaiah 56 >