< Isaiah 56 >

1 Èyí ni ohun ti Olúwa sọ: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.
Ko te kupu tenei a Ihowa, Puritia te whakawa, mahia te tika; no te mea ka tata he putanga mo taku whakaora, he whakakitenga mo toku tika.
2 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”
Ka hari te tangata nana tenei mahi, te tama a te tangata e pupuri nei i a ia, mau tonu; e pupuri ana, a kahore e whakapoke i te hapati, e tiaki ana i tona ringa kei mahi i tetahi he.
3 Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀ mọ́ Olúwa sọ wí pé, “Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.” Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé, “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”
Kaua hoki te tama a te tangata ke, kua hona nei ki a Ihowa, e korero, e mea, He pono ka wehea rawatia mai ahau e Ihowa i roto i tana iwi; kaua ano te unaka e ki, Nana, he rakau maroke ahau.
4 Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí: “Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin
Ko ta Ihowa kupu hoki tenei mo nga unaka e pupuri ana i aku hapati, e whiriwhiri ana i nga mea e paingia ana e ahau, a e hopu ana i taku kawenata;
5 fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀ ìrántí kan àti orúkọ kan tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin, Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé tí a kì yóò ké kúrò.
Ka hoatu e ahau he wahi ki a ratou i roto i toku whare, i roto ano i oku taiepa, he ingoa ano e pai ake ana i o nga tama, i o nga tamahine; he ingoa mau tonu taku e hoatu ai ki a ratou, he mea e kore e hatepea atu.
6 Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa láti sìn ín, láti fẹ́ orúkọ Olúwa àti láti foríbalẹ̀ fún un gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́ àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—
Ko nga tamariki hoki a te tangata ke, kua oti te hono ki a Ihowa, he mea kia mahi ai ratou ki a ia, kia aroha ki te ingoa o Ihowa, kia waiho hei pononga mana; ko te hunga katoa e pupuri ana, a kahore e whakapoke i te hapati, a e hopu ana i taku k awenata;
7 àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi, èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi. Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn, ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi; nítorí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”
Ka kawea ratou e ahau ki toku maunga tapu, ka whakahari ano ahau i a ratou i roto i toku whare inoi; ka manakohia a ratou tahunga tinana, me a ratou patunga tapu i runga i taku aata; no te mea ka kiia toku whare, He whare inoi mo nga iwi katoa.
8 Olúwa Olódùmarè sọ wí pé— ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ: “Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”
He kupu tenei na te Ariki, na Ihowa, na te kaikohikohi mai o te hunga o Iharaira i peia atu, Kua kohikohia era ki a ia; ka kohikohi ano ahau i etahi atu ki a ia.
9 Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá, ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!
E nga kirehe katoa o te parae, haere mai ki te kai, e nga kirehe katoa o te ngahere.
10 Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú, gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀; gbogbo wọn jẹ́ adití ajá, wọn kò lè gbó; wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá, wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.
Ko ona tutei, he matapo katoa, kahore e mohio; he kuri reokore katoa ratou, e kore e tau; he momoe, he takoto, e matenui ana ki te moe.
11 Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀; wọn kì í ní ànító. Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye; olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.
Ae ra, he kuri apo kai ratou, kahore rawa e makona; he hepara enei e kore e ngoto te matauranga; anga katoa ana ratou ki tona ara, ki tona ara, ki te mea taonga mona i tona wahi, i tona wahi.
12 Igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn ni wí pé, “Wá, fún mi ní ọtí wáìnì! Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó ọ̀la yóò sì dàbí òní, tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
Ko ta ratou ki, Haere mai, maku e tiki he waina, kia nui ano ta tatou inu i te wai kaha; a ka rite te ra apopo ki tenei ra, he ra kei runga noa atu tona nui.

< Isaiah 56 >