< Isaiah 55 >

1 “Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ, ẹ wá sí ibi omi; àti ẹ̀yin tí kò ní owó; ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ! Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà láìsí owó àti láìdíyelé.
“Atĩrĩrĩ, inyuĩ inyuothe arĩa mũnyootiĩ-rĩ, ũkaai mũnyue maaĩ; na inyuĩ mũtarĩ na mbeeca-rĩ, ũkaai mũgũre irio, mũrĩe! Ũkaai, mũgũre ndibei na iria mũtarĩ na mbeeca mũkũruta, na hatarĩ na thogora.
2 Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn? Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũtũmĩre mbeeca harĩ irio gũtarĩ, o na mũnoge mũkĩrutĩra wĩra kĩndũ gĩtangĩmũhũũnia? Thikĩrĩriai na mũnjigue, nĩguo mũrĩĩage indo iria njega, nacio ngoro cianyu nĩirĩkenagĩra irio iria njega mũno.
3 Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi; gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè. Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ, ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
Tegai matũ mũthikĩrĩrie, na mũũke kũrĩ niĩ; njiguai nĩgeetha mũtũũre muoyo. Na niĩ nĩngarĩĩkanĩra na inyuĩ kĩrĩkanĩro gĩa gũtũũra tene na tene, arĩ wendo wakwa wa kwĩhokeka ũrĩa nderĩire Daudi.
4 Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn, olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
Atĩrĩrĩ ũcio nĩndĩmũtuĩte mũira kũrĩ ndũrĩrĩ, na ngamũtua mũtongoria na mũnene wa ndũrĩrĩ.
5 Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ Ẹni Mímọ́ Israẹli nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”
Ti-itherũ nĩũgeeta ndũrĩrĩ iria ũtooĩ, nacio ndũrĩrĩ iria itakũũĩ itengʼere ciũke kũrĩ we, nĩ ũndũ wa Jehova Ngai waku, o we Ũrĩa Mũtheru wa Isiraeli, nĩgũkorwo nĩakũhumbĩte ũkengu mũnene.”
6 Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i; ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
Mathaai Jehova hĩndĩ ĩrĩa angĩoneka; mũkaĩrei hĩndĩ ĩrĩa arĩ hakuhĩ.
7 Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀. Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un, àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
Mũndũ ũrĩa mwaganu nĩatigane na mĩthiĩre yake, nake mũndũ ũrĩa ũtarĩ mũthingu atigane na meciiria make mooru. Nĩacookerere Jehova, na nĩekũmũiguĩra tha, na acookerere Ngai witũ, nĩgũkorwo nĩakĩragĩrĩria kũrekanĩra.
8 “Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín, tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,” ni Olúwa wí.
“Nĩgũkorwo meciiria makwa timo meciiria manyu, o na kana mĩthiĩre yanyu ĩgatuĩka ta mĩthiĩre yakwa,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
9 “Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ àti èrò mi ju èrò yín lọ.
“O ta ũrĩa matu maraihanĩrĩirie na thĩ, ũguo noguo mĩthiĩre yakwa ĩraihanĩrĩirie na mĩthiĩre yanyu, o na meciiria makwa magakĩra meciiria manyu.
10 Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín ti wálẹ̀ láti ọ̀run tí kì í sì padà sí ibẹ̀ láì bomirin ilẹ̀ kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
Nĩgũkorwo o ta ũrĩa mbura yuraga, narĩo ira rĩkaharũrũka kuuma igũrũ, na iticookaga kuo itaihũgĩtie thĩ na igatũma mĩmera ĩthundũke na ĩciare, nĩguo mũhandi aheo mbeũ na ũrĩa wendaga kũrĩa aheo irio ciake,
11 bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá; kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́, yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
ũguo noguo kiugo gĩakwa kĩrĩa kiumaga kanua gakwa gĩgaaikara: Kiugo kĩu gĩtikanjookerera o ro ũguo tũhũ, no nĩgĩkahingia ũrĩa nyendete wĩkwo, na gĩkinyanĩrie muoroto ũrĩa watũmire ndĩgĩtũme.
12 Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀ a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà; òkè ńlá ńlá àti kéékèèké yóò bú sí orin níwájú yín àti gbogbo igi inú pápá yóò máa pàtẹ́wọ́.
Ũkoimagara na gĩkeno, na ũthiiage ũtongoretio nĩ thayũ; irĩma o na tũrĩma nacio nĩigaitĩka kũina rwĩmbo mbere yaku, nayo mĩtĩ yothe ya gĩthaka nĩĩkahũũra hĩ.
13 Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà, àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ. Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa, fún àmì ayérayé, tí a kì yóò lè parun.”
Ithenya rĩa mĩigua-rĩ, gũkaamera mĩthengera, na ithenya rĩa congʼe kũmere mĩhandathi. Naguo ũndũ ũcio ũgaatuĩka wa gũtũma Jehova agĩe igweta, na ũtuĩke kĩmenyithia gĩa gũtũũra nginya tene, kĩrĩa gĩtagathũkio.”

< Isaiah 55 >