< Isaiah 55 >

1 “Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ, ẹ wá sí ibi omi; àti ẹ̀yin tí kò ní owó; ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ! Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà láìsí owó àti láìdíyelé.
Vous qui êtes altérés, venez à l'eau; vous qui n'avez point d'argent, allez et achetez; sans argent et sans échange, nourrissez-vous de graisse et de vin.
2 Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn? Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
Pourquoi faites-vous cas de l'argent et vous fatiguez-vous pour ce qui ne rassasie pas? Écoutez-moi, et vous mangerez ce qui est vraiment bon; et votre âme se délectera des vrais biens.
3 Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi; gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè. Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ, ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
Prêtez-moi des oreilles attentives, et suivez mes voies; écoutez-moi, et votre âme vivra des vrais biens, et je ferai avec vous une alliance éternelle, et les promesses faites à David seront vérifiées.
4 Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn, olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
Voilà que j'ai donné aux nations un témoignage; c'est lui, le prince, le maître des Gentils.
5 Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ Ẹni Mímọ́ Israẹli nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”
Des nations qui ne te connaissaient pas t'invoqueront, et des peuples à qui tu étais inconnu se réfugieront auprès de toi, à cause du Seigneur ton Dieu, le Saint d'Israël, parce qu'il t'aura glorifié.
6 Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i; ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
Cherchez le Seigneur, et, quand vous l'aurez trouvé, invoquez-le. Et lorsqu'il sera près de vous,
7 Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀. Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un, àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
Que l'impie quitte ses voies, et le prévaricateur ses conseils; qu'il se convertisse au Seigneur, et il lui sera fait miséricorde, parce qu'il vous remettra beaucoup de péchés.
8 “Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín, tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,” ni Olúwa wí.
Car mes conseils ne sont pas comme vos conseils, ni mes voies comme vos voies, dit le Seigneur.
9 “Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ àti èrò mi ju èrò yín lọ.
Mais autant le ciel est loin de la terre, autant ma voie est loin de vos voies, et vos pensées, loin de ma pensée.
10 Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín ti wálẹ̀ láti ọ̀run tí kì í sì padà sí ibẹ̀ láì bomirin ilẹ̀ kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
Car telle la pluie ou la neige descend du ciel et n'y retournera point avant d'avoir abreuvé la terre et humecté les champs; avant d'avoir produit des graines pour le semeur, et donné du pain pour sa nourriture;
11 bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá; kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́, yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
Telle sera ma parole; toute parole qui sortira de ma bouche ne reviendra point à moi que mes volontés ne soient accomplies; et je ferai prospérer tes voies, et mes ordres auront leur effet.
12 Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀ a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà; òkè ńlá ńlá àti kéékèèké yóò bú sí orin níwájú yín àti gbogbo igi inú pápá yóò máa pàtẹ́wọ́.
Car vous sortirez pleins d'allégresse, et vous serez enseignés dans la joie. Les montagnes et les collines bondiront de joie pour votre bienvenue, et les arbres de la plaine vous applaudiront du bruit de leurs rameaux.
13 Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà, àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ. Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa, fún àmì ayérayé, tí a kì yóò lè parun.”
Où croissaient la mousse et les épines, s'élèveront le myrte et le cyprès. Et le nom du Seigneur sera proclamé, et ce sera un signe éternel, et il ne disparaîtra jamais.

< Isaiah 55 >