< Isaiah 55 >

1 “Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ, ẹ wá sí ibi omi; àti ẹ̀yin tí kò ní owó; ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ! Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà láìsí owó àti láìdíyelé.
« Hé! Venez, tous ceux qui ont soif, vers les eaux! Viens, celui qui n'a pas d'argent, achète et mange! Oui, venez, achetez du vin et du lait sans argent et sans prix.
2 Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn? Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
Pourquoi dépensez-vous de l'argent pour ce qui n'est pas du pain, et votre travail pour ce qui ne satisfait pas? Écoutez-moi attentivement, et mangez ce qui est bon, et laisse ton âme se délecter de richesses.
3 Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi; gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè. Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ, ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
Tourne ton oreille, et viens à moi. Écoutez, et votre âme vivra. Je conclurai avec vous une alliance éternelle, les grâces sûres de David.
4 Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn, olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
Voici, je l'ai donné en témoignage aux peuples, un chef et un commandant pour les peuples.
5 Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ Ẹni Mímọ́ Israẹli nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”
Voici, tu appelleras une nation que tu ne connais pas; et une nation qui ne te connaissait pas courra vers toi, à cause de Yahvé ton Dieu, et pour le Saint d'Israël; car il vous a glorifié. »
6 Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i; ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
Cherchez Yahvé pendant qu'il se trouve. Faites appel à lui pendant qu'il est proche.
7 Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀. Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un, àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
Que le méchant abandonne sa voie, et l'homme injuste ses pensées. Qu'il revienne à Yahvé, et il aura pitié de lui, à notre Dieu, car il pardonne librement.
8 “Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín, tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,” ni Olúwa wí.
« Car mes pensées ne sont pas vos pensées, et vos voies ne sont pas mes voies », dit Yahvé.
9 “Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ àti èrò mi ju èrò yín lọ.
« Car de même que les cieux sont plus élevés que la terre, mes voies sont donc plus élevées que les vôtres, et mes pensées que vos pensées.
10 Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín ti wálẹ̀ láti ọ̀run tí kì í sì padà sí ibẹ̀ láì bomirin ilẹ̀ kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
Car comme la pluie descend et la neige tombe du ciel, et n'y retourne pas, mais arrose la terre, et le fait grandir et bourgeonner, et donne la semence au semeur et le pain à celui qui mange;
11 bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá; kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́, yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
ainsi en est-il de ma parole qui sort de ma bouche: elle ne me reviendra pas vide, mais il accomplira ce qui me plaît, et il prospérera dans ce que je l'ai envoyé faire.
12 Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀ a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà; òkè ńlá ńlá àti kéékèèké yóò bú sí orin níwájú yín àti gbogbo igi inú pápá yóò máa pàtẹ́wọ́.
Car vous sortirez avec joie, et être conduit en paix. Les montagnes et les collines se mettront à chanter devant toi; et tous les arbres des champs battront des mains.
13 Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà, àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ. Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa, fún àmì ayérayé, tí a kì yóò lè parun.”
Au lieu de l'épine, le cyprès s'élèvera; et à la place de l'abricot, le myrte poussera. Il fera un nom à Yahvé, pour un signe éternel qui ne sera pas supprimé. »

< Isaiah 55 >