< Isaiah 54 >

1 “Kọrin, ìwọ obìnrin àgàn, ìwọ tí kò tí ì bímọ rí; bú sí orin, ẹ hó fún ayọ̀, ẹ̀yin tí kò tí ì rọbí rí; nítorí pé púpọ̀ ni ọmọ àwọn obìnrin ìsọdahoro ju ti ẹni tí ó ní ọkọ,” ni Olúwa wí.
E OLI oe, e ka mea pa, ka mea i hanau ole hoi; E oli i ke oli, a e hauoli hoi, e ka mea kuakoko ole; No ka mea, ua nui aku na keiki a ka mea i neoneo, i na keiki a ka wahine i mareia, wahi a Iehova.
2 Fẹ ibi àgọ́ rẹ lójú sí i, fẹ aṣọ àgọ́ rẹ kí ó gbòòrò sí i, má ṣe dá a dúró; sọ okùn rẹ di gígùn, mú òpó rẹ lágbára sí i.
A hoakea i kahi o kou halelewa, E hoopalahalaha hoi lakou i na paku o kou wahi e noho ai; Mai aua, e hooloihi i kou mau kaula, E hoopaa loa hoi i kou mau makia;
3 Nítorí ìwọ ó fẹ̀ sọ́tùn àti sí òsì; ìrandíran rẹ yóò jogún àwọn orílẹ̀-èdè, wọn yóò sì dó sí ahoro àwọn ìlú wọn.
No ka mea, e poha aku auanei oe, ma ka lima akau, a ma ka lima hema; A e ili mai ko na aina na kau poe mamo, A ia lakou no e hoonohoia na kulanakauhale neoneo.
4 “Má ṣe bẹ̀rù, ìtìjú kò ní ṣubú lù ọ́. Má ṣe bẹ̀rù ìdójútì, a kì yóò kàn ọ́ lábùkù. Ìwọ yóò gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe e rẹ, ìwọ kì yóò sì rántí ẹ̀gàn ìgba-opo rẹ mọ́.
Mai makau oe, no ka mea, aole oe e hilahila, Mai hoopalaimaka, no ka mea, aole oe hoohilahilaia; E hoopoina no hoi oe i ka hilahila o kou wa opiopio, Aole hoi e mauao hou i ka hoowahawahaia o kou noho wahine kane make ana.
5 Nítorí Ẹlẹ́dàá rẹ ni ọkọ rẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀ Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà rẹ; a sì ń pè é ní Ọlọ́run gbogbo ayé.
No ka mea, o ka mea nana oe i hana, oia kau kane, O Iehova o na kaua kona inoa; A o kou Hoolapanai, o ka Mea Hemolele ia o ka Iseraela; E kapaia no hoi oia, ke Akua o ka honua a pau.
6 Olúwa yóò pè ọ́ padà àfi bí ẹni pé obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ tí a sì bà lọ́kàn jẹ́ obìnrin tí a fẹ́ ní ọ̀dọ́, tí a sì wá jákulẹ̀,” ni Olúwa wí.
No ka mea, ua hea aku o Iehova ia oe, E like me ka wahine i haaleleia, a kaumaha hoi ma ka naau, Ka wahine hoi i ka wa opiopio; No ka mea, e hooleia oia, wahi a ke Akua ou.
7 “Fún ìgbà díẹ̀ ni mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn ìyọ́nú èmi yóò mú ọ padà wá.
No ka manawa uuku, ua haalele aku au ia oe; Aka, me ka lokomaikai he nui loa, e hoiliili au ia oe.
8 Ní ríru ìbínú. Mo fi ojú pamọ́ fún ọ fún ìṣẹ́jú kan, ṣùgbọ́n pẹ̀lú àánú àìnípẹ̀kun Èmi yóò síjú àánú wò ọ́,” ni Olúwa Olùdáǹdè rẹ wí.
I ka hu ana o ka huhu, huna no wau i ko'u maka ia oe i kekahi minute; Aka, me ke aloha mau loa, e lokomaikai aku ai au ia oe, Wahi a Iehova, kou Hoolapanai.
9 “Sí mi, èyí dàbí i àwọn ọjọ́ Noa, nígbà tí mo búra pé àwọn omi Noa kì yóò tún bo ilẹ̀ ayé mọ́. Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí mo ti búra láti má ṣe bínú sí ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá ọ wí mọ́.
No ka mea, e like me na wai o Noa, pela no keia ia'u; Me au i hoohiki ai, aole e hoohalana hou na wai o Noa i ka honua, Pela no wau i hoohiki ai, aole au e huhu aku ia oe, Aole hoi au e paipai ikaika aku ia oe.
10 Bí a tilẹ̀ mi àwọn òkè ńlá tí a sì ṣí àwọn òkè kékeré nídìí, síbẹ̀síbẹ̀ ìfẹ́ àìkùnà mi fún ọ kì yóò yẹ̀ láéláé tàbí májẹ̀mú àlàáfíà ni a ó mú kúrò,” ni Olúwa, ẹni tí ó síjú àánú wò ọ́ wí.
No ka mea, e lilo auanei na kuahiwi, A e hooneeneeia na mauna; Aka, aole e lilo aku ko'u lokomaikai, Aole hoi e hooneeneeia ka berita o ko'u malu, Wahi a Iehova, ka mea i aloha mai ia oe.
11 Ìwọ ìlú tí a pọ́n lójú, tí ìjì ń gbá kiri tí a kò sì tù nínú, Èmi yóò fi òkúta Tikuosi kọ́ ọ àti ìpìlẹ̀ rẹ pẹ̀lú safire.
E ka mea popilikia i hooalealeia, Aole hoi i alohaia! E hoonoho wau i kou mau pohaku maloko o ka pena, A e hookumu wau ia oe ma ua pohaku sapeiro.
12 Èmi yóò fi iyùn ṣe odi rẹ, àwọn ẹnu-ọ̀nà ni a ó fi ohun èlò dáradára fún, àti àwọn ògiri rẹ pẹ̀lú òkúta iyebíye.
A hana no wau i kou mau puupuu kaua i pohaku paea, A me kou mau pukapa i pohaku ula, A me kou mau mokuna a pau i pohaku maikai.
13 Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ́, àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ́ ńlá àti púpọ̀.
E aoia no hoi kau mau keiki a pau e Iehova, A e nui loa auanei ka pomaikai o kau mau keiki.
14 Ní òdodo ni a ó fi ìdí rẹ kalẹ̀ ìwà ipá yóò jìnnà sí ọ o kò ní bẹ̀rù ohunkóhun, ìpayà la ó mú kúrò pátápátá; kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Ma ka pono no oe e hookumuia'i: E mamao aku oe i ka hookaumaha, No ka mea, aole oe e makau ana; A i ka weliweli hoi, no ka mea, aole ia e hookokoke mai ia oe.
15 Bí ẹnikẹ́ni bá tilẹ̀ bá ọ jà, kò ní jẹ́ láti ọwọ́ mi; ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ọ jà ni yóò túúbá fún ọ.
Aia hoi, e hookipikipi no lakou, aole nae mamuli o ka'u olelo ana, O ka mea kipi aku ia oe, e haule no ia mamuli ou.
16 “Kíyèsi i, èmi ni ó dá alágbẹ̀dẹ tí ń fẹ́ iná èédú iná tí ó sì ń mú ohun èlò wá tí ó bá iṣẹ́ rẹ mu. Èmi náà sì ni ẹni tí ó dá apanirun láti ṣe iṣẹ́ ibi;
Aia hoi, na'u no i hana i ka amara nana e puhi i ka lanahu i ke ahi, A hoopuka mai la oia i mea hana no kana hana; A na'u hoi i hana i ka mea make e make ai.
17 kò sí ohun ìjà tí a ṣe sí ọ tí yóò lè ṣe nǹkan, àti gbogbo ahọ́n tí ó dìde sí ọ ní ìdájọ́ ni ìwọ ó dá ní ẹ̀bi. Èyí ni ogún àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, èyí sì ni ìdáláre wọn láti ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
O na mea hoeha a pau i hanaia e ku e ia oe, aole lakou e lanakila, A o na elelo a pau e ala mai e ku e ia oe, nau no ia e hoahewa aku. Oia ka hooilina o na kanwa a Iehova, A na'u hoi ko lakou pono, wahi a Iehova.

< Isaiah 54 >

A Dove is Sent Forth from the Ark
A Dove is Sent Forth from the Ark