< Isaiah 54 >

1 “Kọrin, ìwọ obìnrin àgàn, ìwọ tí kò tí ì bímọ rí; bú sí orin, ẹ hó fún ayọ̀, ẹ̀yin tí kò tí ì rọbí rí; nítorí pé púpọ̀ ni ọmọ àwọn obìnrin ìsọdahoro ju ti ẹni tí ó ní ọkọ,” ni Olúwa wí.
« Chante, stérile, toi qui n'as pas enfanté! Éclatez en chants, et criez à haute voix, vous qui n'avez pas enfanté! Car les enfants de la désolée sont plus nombreux que les enfants de la femme mariée, dit Yahvé.
2 Fẹ ibi àgọ́ rẹ lójú sí i, fẹ aṣọ àgọ́ rẹ kí ó gbòòrò sí i, má ṣe dá a dúró; sọ okùn rẹ di gígùn, mú òpó rẹ lágbára sí i.
« Élargis le lieu de ta tente, et qu'ils tendent les rideaux de vos habitations; n'épargnez pas; allongez vos cordes, et renforcez vos pieux.
3 Nítorí ìwọ ó fẹ̀ sọ́tùn àti sí òsì; ìrandíran rẹ yóò jogún àwọn orílẹ̀-èdè, wọn yóò sì dó sí ahoro àwọn ìlú wọn.
Car tu t'étendras à droite et à gauche; et ta descendance possédera les nations et s'installent dans des villes désolées.
4 “Má ṣe bẹ̀rù, ìtìjú kò ní ṣubú lù ọ́. Má ṣe bẹ̀rù ìdójútì, a kì yóò kàn ọ́ lábùkù. Ìwọ yóò gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe e rẹ, ìwọ kì yóò sì rántí ẹ̀gàn ìgba-opo rẹ mọ́.
« N'ayez pas peur, car vous n'aurez pas à rougir. Ne vous laissez pas déconcerter, car vous ne serez pas déçu. Car tu oublieras la honte de ta jeunesse. Vous ne vous souviendrez plus de l'opprobre de votre veuvage.
5 Nítorí Ẹlẹ́dàá rẹ ni ọkọ rẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀ Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà rẹ; a sì ń pè é ní Ọlọ́run gbogbo ayé.
Car ton créateur est ton époux; son nom est Yahvé des armées. Le Saint d'Israël est votre rédempteur. Il sera appelé le Dieu de toute la terre.
6 Olúwa yóò pè ọ́ padà àfi bí ẹni pé obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ tí a sì bà lọ́kàn jẹ́ obìnrin tí a fẹ́ ní ọ̀dọ́, tí a sì wá jákulẹ̀,” ni Olúwa wí.
Car Yahvé t'a appelée comme une femme délaissée et affligée en esprit, même une épouse de jeunesse, quand elle est rejetée, » dit votre Dieu.
7 “Fún ìgbà díẹ̀ ni mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn ìyọ́nú èmi yóò mú ọ padà wá.
« Pour un petit moment, je vous ai abandonnés, mais je vous rassemblerai avec une grande miséricorde.
8 Ní ríru ìbínú. Mo fi ojú pamọ́ fún ọ fún ìṣẹ́jú kan, ṣùgbọ́n pẹ̀lú àánú àìnípẹ̀kun Èmi yóò síjú àánú wò ọ́,” ni Olúwa Olùdáǹdè rẹ wí.
Dans une colère débordante, je t'ai caché ma face pendant un instant, mais j'aurai pitié de toi avec une bonté éternelle, dit Yahvé ton Rédempteur.
9 “Sí mi, èyí dàbí i àwọn ọjọ́ Noa, nígbà tí mo búra pé àwọn omi Noa kì yóò tún bo ilẹ̀ ayé mọ́. Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí mo ti búra láti má ṣe bínú sí ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá ọ wí mọ́.
« Car ceci est pour moi comme les eaux de Noé; car j'ai juré que les eaux de Noé ne passeraient plus sur la terre, J'ai donc juré que je ne me mettrai pas en colère contre vous et que je ne vous réprimanderai pas.
10 Bí a tilẹ̀ mi àwọn òkè ńlá tí a sì ṣí àwọn òkè kékeré nídìí, síbẹ̀síbẹ̀ ìfẹ́ àìkùnà mi fún ọ kì yóò yẹ̀ láéláé tàbí májẹ̀mú àlàáfíà ni a ó mú kúrò,” ni Olúwa, ẹni tí ó síjú àánú wò ọ́ wí.
Car les montagnes peuvent s'éloigner, et que les collines soient enlevées, mais ma bonté ne se retirera pas de toi, et mon alliance de paix ne sera pas retirée, » dit Yahvé qui a pitié de vous.
11 Ìwọ ìlú tí a pọ́n lójú, tí ìjì ń gbá kiri tí a kò sì tù nínú, Èmi yóò fi òkúta Tikuosi kọ́ ọ àti ìpìlẹ̀ rẹ pẹ̀lú safire.
« Vous êtes affligés, ballottés par les tempêtes, et vous n'êtes pas consolés, Voici, je vais sertir vos pierres de belles couleurs, et posez vos fondations avec des saphirs.
12 Èmi yóò fi iyùn ṣe odi rẹ, àwọn ẹnu-ọ̀nà ni a ó fi ohun èlò dáradára fún, àti àwọn ògiri rẹ pẹ̀lú òkúta iyebíye.
Je ferai de tes pinacles des rubis, vos portes de joyaux étincelants, et tous tes murs de pierres précieuses.
13 Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ́, àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ́ ńlá àti púpọ̀.
Tous vos enfants seront instruits par Yahvé, et la paix de vos enfants sera grande.
14 Ní òdodo ni a ó fi ìdí rẹ kalẹ̀ ìwà ipá yóò jìnnà sí ọ o kò ní bẹ̀rù ohunkóhun, ìpayà la ó mú kúrò pátápátá; kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Tu seras établi dans la justice. Vous serez loin de l'oppression, car vous n'aurez pas peur, et loin de la terreur, car il ne s'approchera pas de toi.
15 Bí ẹnikẹ́ni bá tilẹ̀ bá ọ jà, kò ní jẹ́ láti ọwọ́ mi; ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ọ jà ni yóò túúbá fún ọ.
Voici, ils peuvent s'assembler, mais pas par moi. Celui qui se ligue contre toi tombera à cause de toi.
16 “Kíyèsi i, èmi ni ó dá alágbẹ̀dẹ tí ń fẹ́ iná èédú iná tí ó sì ń mú ohun èlò wá tí ó bá iṣẹ́ rẹ mu. Èmi náà sì ni ẹni tí ó dá apanirun láti ṣe iṣẹ́ ibi;
« Voici, j'ai créé le forgeron qui attise les charbons pour les enflammer, et forge une arme pour son travail; et j'ai créé le destructeur pour détruire.
17 kò sí ohun ìjà tí a ṣe sí ọ tí yóò lè ṣe nǹkan, àti gbogbo ahọ́n tí ó dìde sí ọ ní ìdájọ́ ni ìwọ ó dá ní ẹ̀bi. Èyí ni ogún àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, èyí sì ni ìdáláre wọn láti ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
Aucune arme formée contre toi ne prévaudra; et vous condamnerez en jugement toute langue qui s'élèvera contre vous. Tel est l'héritage des serviteurs de Yahvé, et leur justice vient de moi », dit Yahvé.

< Isaiah 54 >

A Dove is Sent Forth from the Ark
A Dove is Sent Forth from the Ark