< Isaiah 54 >
1 “Kọrin, ìwọ obìnrin àgàn, ìwọ tí kò tí ì bímọ rí; bú sí orin, ẹ hó fún ayọ̀, ẹ̀yin tí kò tí ì rọbí rí; nítorí pé púpọ̀ ni ọmọ àwọn obìnrin ìsọdahoro ju ti ẹni tí ó ní ọkọ,” ni Olúwa wí.
Yahweh says, “You [people of Jerusalem] [MET], start to sing! You [who are like] [MET] women who have never given birth to children, sing loudly and shout joyfully, because you, [who are like] [MET] childless women who have been abandoned [by their husbands], will [soon] have more children than women who have never had any children.
2 Fẹ ibi àgọ́ rẹ lójú sí i, fẹ aṣọ àgọ́ rẹ kí ó gbòòrò sí i, má ṣe dá a dúró; sọ okùn rẹ di gígùn, mú òpó rẹ lágbára sí i.
Make your tents larger; make them wider, and fasten them firmly with tent pegs.
3 Nítorí ìwọ ó fẹ̀ sọ́tùn àti sí òsì; ìrandíran rẹ yóò jogún àwọn orílẹ̀-èdè, wọn yóò sì dó sí ahoro àwọn ìlú wọn.
[You will need to make your city much larger] because [soon] you and your descendants will spread all over the land. They will force the people of [other] nations [who now live in your cities] to leave, and you will live [again] in those cities [that were previously abandoned].
4 “Má ṣe bẹ̀rù, ìtìjú kò ní ṣubú lù ọ́. Má ṣe bẹ̀rù ìdójútì, a kì yóò kàn ọ́ lábùkù. Ìwọ yóò gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe e rẹ, ìwọ kì yóò sì rántí ẹ̀gàn ìgba-opo rẹ mọ́.
Do not be afraid; you will no [longer] be ashamed. Previously you were ashamed [because your enemies conquered you] and caused many of your women to become widows, but [soon] you will not even remember that.
5 Nítorí Ẹlẹ́dàá rẹ ni ọkọ rẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀ Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà rẹ; a sì ń pè é ní Ọlọ́run gbogbo ayé.
[I], the Commander of the armies of angels, the Holy one of Israel, who rules over the whole earth, the one who created you, will be [like] [MET] a husband to you.
6 Olúwa yóò pè ọ́ padà àfi bí ẹni pé obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ tí a sì bà lọ́kàn jẹ́ obìnrin tí a fẹ́ ní ọ̀dọ́, tí a sì wá jákulẹ̀,” ni Olúwa wí.
You were like a woman whose husband left her, and caused you to be very sad; you were like a young woman who got married when she was [very] young, and then her husband abandoned her.
7 “Fún ìgbà díẹ̀ ni mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn ìyọ́nú èmi yóò mú ọ padà wá.
I abandoned you [people of Jerusalem] for a while, but [now] I am saying, ‘I will take you back.’
8 Ní ríru ìbínú. Mo fi ojú pamọ́ fún ọ fún ìṣẹ́jú kan, ṣùgbọ́n pẹ̀lú àánú àìnípẹ̀kun Èmi yóò síjú àánú wò ọ́,” ni Olúwa Olùdáǹdè rẹ wí.
I was very angry with you for a while, and I turned away from you. But I will act mercifully toward you and I will faithfully love you forever. That is what [I], Yahweh, your protector, say to you.
9 “Sí mi, èyí dàbí i àwọn ọjọ́ Noa, nígbà tí mo búra pé àwọn omi Noa kì yóò tún bo ilẹ̀ ayé mọ́. Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí mo ti búra láti má ṣe bínú sí ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá ọ wí mọ́.
During the time that Noah lived, I solemnly promised that I would never again allow a flood to cover the earth. So [now] I solemnly promise that I will not be angry with you again and (rebuke you/threaten to punish you).
10 Bí a tilẹ̀ mi àwọn òkè ńlá tí a sì ṣí àwọn òkè kékeré nídìí, síbẹ̀síbẹ̀ ìfẹ́ àìkùnà mi fún ọ kì yóò yẹ̀ láéláé tàbí májẹ̀mú àlàáfíà ni a ó mú kúrò,” ni Olúwa, ẹni tí ó síjú àánú wò ọ́ wí.
Even if the mountains and hills shake and collapse, I will not stop faithfully loving you, and I will not cancel my agreement to cause things to go well for you. That is what [I], Yahweh, who act mercifully, say.
11 Ìwọ ìlú tí a pọ́n lójú, tí ìjì ń gbá kiri tí a kò sì tù nínú, Èmi yóò fi òkúta Tikuosi kọ́ ọ àti ìpìlẹ̀ rẹ pẹ̀lú safire.
You [people of Jerusalem] [APO], [your enemies acted very violently toward you]; [it was as though] your city was battered by a severe storm, and no one helped you. But [now] I will cause your city to be rebuilt with stones made of (turquoise/valuable stones), and I will cause the foundations of the city to be made of (sapphires/valuable blue stones).
12 Èmi yóò fi iyùn ṣe odi rẹ, àwọn ẹnu-ọ̀nà ni a ó fi ohun èlò dáradára fún, àti àwọn ògiri rẹ pẹ̀lú òkúta iyebíye.
I will cause the towers on the city wall to be made of (rubies/valuable red stones), and all the gates of the city will be made of [other] very valuable stones.
13 Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ́, àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ́ ńlá àti púpọ̀.
I will be the one who will teach you people and cause things to go well with you.
14 Ní òdodo ni a ó fi ìdí rẹ kalẹ̀ ìwà ipá yóò jìnnà sí ọ o kò ní bẹ̀rù ohunkóhun, ìpayà la ó mú kúrò pátápátá; kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Your [government] will be strong because of acting justly/fairly; no one will (oppress you/cause you to suffer); you will not be afraid, because there will be nothing [PRS] that will (terrorize you/cause you to become extremely afraid).
15 Bí ẹnikẹ́ni bá tilẹ̀ bá ọ jà, kò ní jẹ́ láti ọwọ́ mi; ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ọ jà ni yóò túúbá fún ọ.
If any army attacks you, it will not be because I have incited them to do that, and you will defeat any group that attacks you.
16 “Kíyèsi i, èmi ni ó dá alágbẹ̀dẹ tí ń fẹ́ iná èédú iná tí ó sì ń mú ohun èlò wá tí ó bá iṣẹ́ rẹ mu. Èmi náà sì ni ẹni tí ó dá apanirun láti ṣe iṣẹ́ ibi;
Think about this: (Blacksmiths/Men who make things from metal) fan the coals to make a very hot flame in order to produce weapons that can be used [in battles], but I am the one who has produced blacksmiths! And I am also the one who created people who destroy [other people and cities].
17 kò sí ohun ìjà tí a ṣe sí ọ tí yóò lè ṣe nǹkan, àti gbogbo ahọ́n tí ó dìde sí ọ ní ìdájọ́ ni ìwọ ó dá ní ẹ̀bi. Èyí ni ogún àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, èyí sì ni ìdáláre wọn láti ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
[But I am promising you that I will] not allow you to be defeated/injured by soldiers using weapons that have been made to attack you, and when others try to accuse you, you will (refute them/show that they are wrong). That is the reward that I will give to the people who serve me; I will defend them; that is what [I], Yahweh, promise.”