< Isaiah 54 >

1 “Kọrin, ìwọ obìnrin àgàn, ìwọ tí kò tí ì bímọ rí; bú sí orin, ẹ hó fún ayọ̀, ẹ̀yin tí kò tí ì rọbí rí; nítorí pé púpọ̀ ni ọmọ àwọn obìnrin ìsọdahoro ju ti ẹni tí ó ní ọkọ,” ni Olúwa wí.
Prozpěvuj, neplodná, kteráž nerodíš, zvučně prozpěvuj a prokřikni, kteráž ku porodu nepracuješ, nebo více bude synů opuštěné, nežli synů té, kteráž má muže, praví Hospodin.
2 Fẹ ibi àgọ́ rẹ lójú sí i, fẹ aṣọ àgọ́ rẹ kí ó gbòòrò sí i, má ṣe dá a dúró; sọ okùn rẹ di gígùn, mú òpó rẹ lágbára sí i.
Rozšiř místo stanu svého, a čalounů příbytků svých roztáhnouti nezbraňuj; natáhni i provazů svých, a kolíky své utvrď.
3 Nítorí ìwọ ó fẹ̀ sọ́tùn àti sí òsì; ìrandíran rẹ yóò jogún àwọn orílẹ̀-èdè, wọn yóò sì dó sí ahoro àwọn ìlú wọn.
Nebo na pravo i na levo se rozmůžeš, a símě tvé národy dědičně vládnouti bude, a města pustá osadí.
4 “Má ṣe bẹ̀rù, ìtìjú kò ní ṣubú lù ọ́. Má ṣe bẹ̀rù ìdójútì, a kì yóò kàn ọ́ lábùkù. Ìwọ yóò gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe e rẹ, ìwọ kì yóò sì rántí ẹ̀gàn ìgba-opo rẹ mọ́.
Nebojž se, nebo nebudeš zahanbena, aniž se zapyřuj, nebo nebudeš v potupu uvedena; nýbrž na potupu mladosti své zapomeneš, a na pohanění vdovství svého nezpomeneš více.
5 Nítorí Ẹlẹ́dàá rẹ ni ọkọ rẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀ Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà rẹ; a sì ń pè é ní Ọlọ́run gbogbo ayé.
Nebo manželem tvým jest Učinitel tvůj, jehož jméno Hospodin zástupů, a vykupitel tvůj Svatý Izraelský Bohem vší země slouti bude.
6 Olúwa yóò pè ọ́ padà àfi bí ẹni pé obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ tí a sì bà lọ́kàn jẹ́ obìnrin tí a fẹ́ ní ọ̀dọ́, tí a sì wá jákulẹ̀,” ni Olúwa wí.
Nebo jako ženy propuštěné a v duchu sevřené povolá tě Hospodin, a jako ženy mladice, když v pohrdnutí budeš, praví Bůh tvůj.
7 “Fún ìgbà díẹ̀ ni mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ọkàn ìyọ́nú èmi yóò mú ọ padà wá.
Na maličkou chvilku poopustil jsem tě, ale v slitování převelikém shromáždím tě.
8 Ní ríru ìbínú. Mo fi ojú pamọ́ fún ọ fún ìṣẹ́jú kan, ṣùgbọ́n pẹ̀lú àánú àìnípẹ̀kun Èmi yóò síjú àánú wò ọ́,” ni Olúwa Olùdáǹdè rẹ wí.
V maličkém hněvě skryl jsem tvář svou na maličko před tebou, ale v milosrdenství věčném slituji se nad tebou, praví vykupitel tvůj Hospodin.
9 “Sí mi, èyí dàbí i àwọn ọjọ́ Noa, nígbà tí mo búra pé àwọn omi Noa kì yóò tún bo ilẹ̀ ayé mọ́. Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí mo ti búra láti má ṣe bínú sí ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá ọ wí mọ́.
Neboť jest to u mne, co při potopě Noé. Jakož jsem přisáhl, že se nebudou více rozlévati vody Noé po zemi, tak jsem přisáhl, že se nerozhněvám na tě, aniž tobě přísně domlouvati budu.
10 Bí a tilẹ̀ mi àwọn òkè ńlá tí a sì ṣí àwọn òkè kékeré nídìí, síbẹ̀síbẹ̀ ìfẹ́ àìkùnà mi fún ọ kì yóò yẹ̀ láéláé tàbí májẹ̀mú àlàáfíà ni a ó mú kúrò,” ni Olúwa, ẹni tí ó síjú àánú wò ọ́ wí.
A byť se i hory pohybovaly, a pahrbkové ustupovali, milosrdenství mé však od tebe neodstoupí, a smlouva pokoje mého se nepohne, praví slitovník tvůj Hospodin.
11 Ìwọ ìlú tí a pọ́n lójú, tí ìjì ń gbá kiri tí a kò sì tù nínú, Èmi yóò fi òkúta Tikuosi kọ́ ọ àti ìpìlẹ̀ rẹ pẹ̀lú safire.
Ó ssoužená, vichřicí zmítaná, potěšení zbavená, aj, já položím na karbunkulích kamení tvé, a založím tě na zafiřích.
12 Èmi yóò fi iyùn ṣe odi rẹ, àwọn ẹnu-ọ̀nà ni a ó fi ohun èlò dáradára fún, àti àwọn ògiri rẹ pẹ̀lú òkúta iyebíye.
A vzdělám z křištálu skla tvá, a brány tvé z kamení třpytícího se, i všecka pomezí tvá z kamení drahého.
13 Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ́, àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ́ ńlá àti púpọ̀.
Synové pak tvoji všickni vyučení budou od Hospodina, a hojnost pokoje budou míti synové tvoji.
14 Ní òdodo ni a ó fi ìdí rẹ kalẹ̀ ìwà ipá yóò jìnnà sí ọ o kò ní bẹ̀rù ohunkóhun, ìpayà la ó mú kúrò pátápátá; kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Na spravedlnosti upevněna budeš. Vzdálíš se od ssoužení, protož se ho nebudeš báti, a od setření, nebo nepřiblíží se k tobě.
15 Bí ẹnikẹ́ni bá tilẹ̀ bá ọ jà, kò ní jẹ́ láti ọwọ́ mi; ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ọ jà ni yóò túúbá fún ọ.
Aj, budouť nejedni bydliti s tebou, kteříž nejsou moji, ale kdož by bydleje s tebou, byl proti tobě, padne.
16 “Kíyèsi i, èmi ni ó dá alágbẹ̀dẹ tí ń fẹ́ iná èédú iná tí ó sì ń mú ohun èlò wá tí ó bá iṣẹ́ rẹ mu. Èmi náà sì ni ẹni tí ó dá apanirun láti ṣe iṣẹ́ ibi;
Aj, já stvořil jsem kováře dýmajícího při ohni na uhlí, a vynášejícího nádobí k dílu svému, já také stvořil jsem zhoubce, aby hubil.
17 kò sí ohun ìjà tí a ṣe sí ọ tí yóò lè ṣe nǹkan, àti gbogbo ahọ́n tí ó dìde sí ọ ní ìdájọ́ ni ìwọ ó dá ní ẹ̀bi. Èyí ni ogún àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, èyí sì ni ìdáláre wọn láti ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
Žádný nástroj proti tobě udělaný nepodaří se, a každý jazyk, povstávající proti tobě na soudu, potupíš. Toť jest dědictví služebníků Hospodinových, a spravedlnost jejich ode mne, praví Hospodin.

< Isaiah 54 >

A Dove is Sent Forth from the Ark
A Dove is Sent Forth from the Ark