< Isaiah 52 >

1 Jí, jí, ìwọ Sioni, wọ ara rẹ ní agbára. Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀, ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́ n nì. Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́ kì yóò wọ inú rẹ mọ́.
Trezeşte-te, trezeşte-te; îmbracă-ţi tăria, Sioane; îmbracă-te cu hainele tale frumoase, Ierusalime, cetate sfântă, fiindcă de acum înainte nu vor mai veni în tine cei necircumcişi şi necuraţi.
2 Gbọn eruku rẹ kúrò; dìde sókè, kí o sì gúnwà, ìwọ Jerusalẹmu. Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò, ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbèkùn Sioni.
Scutură-te de praf; ridică-te [şi] şezi jos, Ierusalime, dezleagă-te de legăturile gâtului tău, tu, cea captivă, fiică a Sionului.
3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́, láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà.”
Fiindcă astfel spune DOMNUL: V-aţi vândut pentru nimic; şi veţi fi răscumpăraţi fără bani.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí. “Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti gbé; láìpẹ́ ni Asiria pọ́n wọn lójú.
Fiindcă astfel spune Domnul DUMNEZEU: Poporul meu a coborât înainte în Egipt pentru a locui temporar acolo; şi asirianul l-a oprimat fără motiv.
5 “Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?” ni Olúwa wí. “Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́, àwọn tí ó sì ń jẹ ọba lórí wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,” ni Olúwa wí. “Àti ní ọjọọjọ́ orúkọ mi ni asọ̀rọ̀-òdì sí nígbà gbogbo.
De aceea acum, ce am eu [de făcut] aici, spune DOMNUL, când poporul meu este luat pentru nimic? Cei ce conduc peste ei îi fac să urle, spune DOMNUL; şi numele meu este blasfemiat continuu în fiecare zi.
6 Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi; nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni ó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni.”
De aceea poporul meu va cunoaşte numele meu, de aceea vor cunoaşte în acea zi că eu sunt cel care vorbeşte, iată-mă.
7 Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìnrere ayọ̀ wá, tí wọ́n kéde àlàáfíà, tí ó mú ìyìnrere wá, tí ó kéde ìgbàlà, tí ó sọ fún Sioni pé, “Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!”
Cât de frumoase sunt pe munţi picioarele celui ce aduce veşti bune, care anunţă pace; care aduce veştile bune ale [facerii] binelui, care rosteşte salvarea; care spune Sionului: Dumnezeul tău domneşte!
8 Tẹ́tí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn sókè wọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀. Nígbà tí Olúwa padà sí Sioni, wọn yóò rí i pẹ̀lú ojú u wọn.
Paznicii tăi vor ridica vocea; cu vocea vor cânta împreună, fiindcă vor vedea ochi către ochi, când DOMNUL va aduce din nou Sionul.
9 Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀, ẹ̀yin ahoro Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú, ó sì ti ra Jerusalẹmu padà.
Izbucniţi de bucurie, cântaţi împreună, voi locuri risipite ale Ierusalimului, căci DOMNUL a mângâiat pe poporul său, a răscumpărat Ierusalimul.
10 Olúwa yóò ṣí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀ ní ojú gbogbo orílẹ̀-èdè, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò rí ìgbàlà Ọlọ́run wa.
DOMNUL şi-a dezgolit braţul sfânt în ochii tuturor naţiunilor; şi toate marginile pământului vor vedea salvarea Dumnezeului nostru.
11 Ẹ túká, ẹ túká, ẹ jáde kúrò níhìn-ín yìí! Ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan! Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ kí ẹ sì di mímọ́, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò Olúwa.
Plecaţi, plecaţi, ieşiţi de aici, nu atingeţi nimic necurat; ieşiţi de acolo; fiţi curaţi, cei care purtaţi vasele DOMNULUI.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò yára kúrò tàbí kí ẹ sáré lọ; nítorí Olúwa ni yóò síwájú yín lọ, Ọlọ́run Israẹli ni yóò sì ṣe ààbò lẹ́yìn ín yín.
Fiindcă nu veţi ieşi cu grabă, nici nu veţi merge în zbor, căci DOMNUL va merge înaintea voastră; şi Dumnezeul lui Israel va fi ariergarda voastră.
13 Kíyèsi i, ìránṣẹ́ mi yóò hùwà ọlọ́gbọ́n; òun ni a ó gbé sókè tí a ó sì gbéga a ó sì gbé e lékè gidigidi.
Iată, servitorul meu se va purta cu chibzuinţă, va fi înălţat şi preamărit şi va fi foarte sus.
14 Gẹ́gẹ́ bí a ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń bu ọlá fún un— ìwò ojú rẹ ni a ti bàjẹ́ kọjá ti ẹnikẹ́ni àti ìrísí rẹ̀ ní a ti bàjẹ́ kọjá ohun tí ènìyàn ń fẹ́.
Cât de mulţi au fost înmărmuriţi de tine; atât de desfigurată i-a fost faţa, mai mult decât a oricărui om, şi înfăţişarea lui mai mult decât a fiilor oamenilor;
15 Bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe bomirin àwọn orílẹ̀-èdè ká, àwọn ọba yóò sì pa ẹnu wọn mọ́ nítorí rẹ̀. Nítorí ohun tí a kò sọ fún wọn, wọn yóò rí i, àti ohun tí wọn kò tí ì gbọ́, ni yóò sì yé wọn.
Astfel el va stropi multe naţiuni; înaintea lui împăraţii îşi vor închide gurile, fiindcă vor vedea ceea ce nu li s-a spus; şi vor lua aminte la ceea ce nu au auzit.

< Isaiah 52 >