< Isaiah 51 >
1 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa. Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
Klausāties uz Mani, kas taisnībai dzenaties pakaļ, kas To Kungu meklējat. Uzlūkojiet to akmens kalnu, no kā esat cirsti, un to akas bedri, kur esat izrakti.
2 ẹ wo Abrahamu baba yín, àti Sara, ẹni tó bí i yín. Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni, Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Uzlūkojiet Ābrahāmu, savu tēvu, un Sāru, kas jūs dzemdējusi. To Es aicināju, kad viņš vēl bija viens pats, un Es to svētīju un vairoju.
3 Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀; Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni, àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa. Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀, ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.
Jo Tas Kungs iepriecinās Ciānu, Viņš iepriecinās visas viņas tukšās vietas un darīs viņas tuksnesi kā Edeni un viņas lauku kā Tā Kunga dārzu; prieku un līksmību tur atradīs, pateikšanu un slavas dziesmas.
4 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi; gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi. Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá; ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
Ņem Mani vērā, Mana tauta, atgriežat ausis pie Manis, Mani ļaudis, jo no Manis iziet bauslība, un Savu tiesu Es iecelšu tautām par gaišumu.
5 Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan, ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà, àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá sí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn erékùṣù yóò wò mí wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
Mana taisnība ir tuvu klāt, Mana pestīšana parādās, un Mans elkonis sodīs tautas. Uz Mani salas gaida un cerē uz Manu elkoni.
6 Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run, wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀; àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín, ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin. Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé, òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.
Paceliet savas acis uz debesīm un skatāties uz zemi apakšā; jo debesis iznīks kā dūmi, un zeme nodils kā drēbe, un viņas iedzīvotāji nomirs kā mušas. Bet Mana pestīšana pastāvēs mūžīgi, Mana taisnība netiks apgāzta.
7 “Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́, ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
Klausāties uz Mani, kas taisnību pazīstat, ļaudis, kam Mana bauslība ir sirdī. Nebīstaties par cilvēku nievāšanu un neiztrūcinājāties no viņu zaimošanām.
8 Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ, ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé, àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”
Jo tārpi tos ēdīs kā drēbi, un kodes tos sakapās kā vilnu, bet Mana taisnība pastāvēs mūžīgi un Mana pestīšana uz cilšu ciltīm.
9 Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára ìwọ apá Olúwa; dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì, àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́. Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́ tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
Uzmosties, uzmosties, apvelc stiprumu, Tā Kunga elkonis, uzmosties kā sendienās, vecu vecos laikos! Vai Tu neesi tas, kas Rahabu (Ēģipti) pāršķēlis un to pūķi nodūris?
10 Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí àti àwọn omi inú ọ̀gbun, tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
Vai Tu neesi, kas jūru darījis sausu, tos lielos ūdeņu dziļumus darījis par ceļu, ka tie atpestītie gāja cauri?
11 Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ; ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn. Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.
Un Tā Kunga atpirktie griezīsies atpakaļ un nāks uz Ciānu ar gavilēšanu, un mūžīga līksmība būs pār viņu galvām; prieks un līksmība tos apkamps, skumjas un bēdas bēgs projām.
12 “Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú. Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara, àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
Es, Es esmu jūsu iepriecinātājs: kas tu esi, ka bīsties no cilvēkiem, kam jāmirst, un no cilvēku bērniem, kas iznīkst kā zāle,
13 tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ, ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́ nítorí ìbínú àwọn aninilára, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun? Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
Un aizmirsti To Kungu, savu Radītāju, kas debesis izpletis un zemi dibinājis, un bīsties bez mitēšanās cauru dienu no spaidītāja bardzības, kad tas taisās maitāt? Bet kur nu ir tā spaidītāja bardzība?
14 Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ wọn kò ní kú sínú túbú wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
Steigšus saslēgtais tiek svabads un nenomirs bedrē, un maizes viņam netrūks.
15 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Jo Es esmu Tas Kungs, tavs Dievs, kas kustina jūru, ka viņas viļņi kauc: Kungs Cebaot ir Viņa vārds.
16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́, Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀, ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀, àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’”
Un Es lieku Savus vārdus tavā mutē un tevi apklāju ar Savas rokas ēnu, ka Es dēstu debesis un stādu zemi un saku uz Ciānu: tu esi Mana tauta.
17 Jí, jí! Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu, ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa ago ìbínú rẹ̀, ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Uzmosties, uzmosties, celies Jeruzāleme, kas no Tā Kunga rokas esi dzērusi Viņa bardzības biķeri; reibuma biķeri tu esi izdzērusi un izsūkusi.
18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́ kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
No visiem bērniem, ko tā ir dzemdējusi, neviena nebija, kas viņu būtu vadījis(drošībā un miera vietā), un no visiem bērniem, ko tā uzaudzinājusi, neviena, kas viņu pie rokas būtu ņēmis.
19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ— ta ni yóò tù ọ́ nínú? Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
Šīs divējas lietas tev ir notikušas, kas tad tevi žēlos? Posts un nelaime un bads un zobens, kas tad tevi var iepriecināt?
20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú; wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà, gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n. Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́ àti ìbáwí Ọlọ́run yín.
Tavi bērni pamiruši, tie guļ uz visu ielu stūriem kā stirna tīklā, tie bija pilni Tā Kunga bardzības, tava Dieva draudu.
21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́, tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì.
Tāpēc klausies jel šo, tu apbēdinātā un apreibusī, bet ne no vīna.
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí, Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́, “Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n; láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi, ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
Tā saka tavs Kungs, Tas Kungs, un tavs Dievs, kas Saviem ļaudīm tiesu nesīs: redzi, Es ņemu no tavas rokas to reibuma biķeri, Savas bardzības biķeri, tev vairs to nebūs dzert.
23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’ Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”
Bet Es to došu rokā taviem spaidītājiem, kas uz tavu dvēseli saka: lokies, ka mēs ejam pāri, un noliec savu muguru pār zemi un par ielu tiem, kas staigā pāri.